< Isaiah 36 >
1 Ní ọdún kẹrìnlá ìjọba Hesekiah, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo àwọn ìlú olódi ní ilẹ̀ Juda ó sì kó gbogbo wọn.
Or il arriva la quatorzième année du Roi Ezéchias, que Sennachérib, Roi des Assyriens, monta contre toutes les villes closes de Juda, et les prit.
2 Lẹ́yìn náà, ọba Asiria rán olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Nígbà tí ọ̀gágun náà dúró níbi ojúṣàn adágún ti apá òkè, ní ojú ọ̀nà sí pápá alágbàfọ̀,
Puis le roi des Assyriens envoya Rabsaké avec de grandes forces de Lachis à Jérusalem, vers le roi Ezéchias, et il se présenta près du conduit du haut étang, au grand chemin du champ du foulon.
3 Ṣebna Eliakimu ọmọ Hilkiah alábojútó ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé jáde lọ pàdé rẹ̀.
Et Eliakim, fils de Hilkija, Maître d'hôtel, et Sebna le Secrétaire, et Joab fils d'Asaph, commis sur les registres, sortirent vers lui.
4 Ọ̀gágun náà sọ fún wọn wí pé, “Ẹ sọ fún Hesekiah, “‘Èyí yìí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ pé: Lórí i kí ni ìwọ gbé ìgbẹ́kẹ̀lé tìrẹ yìí lé?
Et Rabsaké leur dit; dites maintenant à Ezéchias; ainsi dit le grand Roi, le Roi des Assyriens; quelle [est] cette confiance que tu as?
5 Ìwọ sọ wí pé ìwọ ní ète àti agbára ogun—ṣùgbọ́n ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ asán. Ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tí ìwọ fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi?
Je te dis que ce ne sont là que des paroles; [mais] le conseil et la force sont requis à la guerre: or maintenant sur qui t'es-tu confié, que tu te sois rebellé contre moi?
6 Wò ó nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti ẹ̀rún igi ọ̀pá lásán tí í gún ni lọ́wọ́ tí í sì í dọ́gbẹ́ sí ni lára tí a bá gbára lé e! Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti sí àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé e.
Voici, tu t'es confié sur ce bâton qui n'est qu'un roseau cassé, sur l'Egypte, sur lequel si quelqu'un s'appuie, il lui entrera dans la main, et la percera; tel est Pharaon Roi d'Egypte à tous ceux qui se confient en lui.
7 Bí o bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run wa,” kì í ṣe òun ni Hesekiah ti mú àwọn ibi gíga àti pẹpẹ rẹ̀ kúrò, tí ó sì wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí”?
Que si tu me dis; nous nous confions en l'Eternel, notre Dieu; n'est-ce pas celui-là même duquel Ezéchias a ôté les hauts lieux et les autels, et a dit à Juda et à Jérusalem; vous vous prosternerez devant cet autel-ci?
8 “‘Ẹ wá nísinsin yìí, bá ọ̀gá mi pa ìmọ̀ pọ̀, ọba Asiria, èmi yóò fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin bí ìwọ bá le è fi agẹṣin lé wọn lórí!
Maintenant donc donne des otages au Roi des Assyriens mon maître; et je te donnerai deux mille chevaux, si tu peux donner autant d'hommes pour monter dessus.
9 Báwo ni ẹ ṣe lè lé ẹyọ kan ṣoṣo padà nínú èyí tí ó kéré jù nínú àwọn balógun olúwa mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti fún kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin?
Et comment ferais-tu tourner visage au moindre gouverneur d'entre les serviteurs de mon maître? mais tu te confies en l'Egypte, à cause des chariots, et des gens de cheval.
10 Síwájú sí i, ǹjẹ́ mo wa lè wá bá ilẹ̀ yìí jà kí n sì pa á run láìsí Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ ló sọ pé kí n bá orílẹ̀-èdè yìí jà kí n sì pa á run.’”
Mais suis-je maintenant monté sans l'Eternel contre ce pays pour le détruire? L'Eternel m'a dit; monte contre ce pays-là, et le détruis.
11 Lẹ́yìn náà ni Eliakimu, Ṣebna àti Joah sọ fún ọ̀gágun náà pé, “Jọ̀wọ́ máa bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀ ní èdè Aramaiki, nítorí pé àwa gbọ́ ọ. Má ṣe bá wa sọ̀rọ̀ ní èdè Heberu ní etí àwọn ènìyàn tí ó wà lórí ògiri mọ́.”
Alors Eliakim, et Sebna, et Joab dirent à Rabsaké; nous te prions de parler en langue syriaque à tes serviteurs, car nous l'entendons; mais ne parle point à nous en langue Judaïque, pendant que le peuple, qui est sur la muraille, l'écoute.
12 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
Et Rabsaké répondit; mon maître m'a-t-il envoyé vers ton maître, ou vers toi, pour dire ces paroles-là? ne m'a-t-il pas envoyé vers les hommes qui se tiennent sur la muraille, pour leur dire qu'ils mangeront leur propre fiente, et qu'ils boiront leur urine avec vous?
13 Lẹ́yìn náà ni ọ̀gágun náà dìde tí ó sì ké síta ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
Rabsaké donc se dressa, et s'écria à haute voix en langue Judaïque, et dit; écoutez les paroles du grand Roi, le Roi des Assyriens.
14 Ohun tí ọba wí nìyìí, Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn yín jẹ. Òun kò le è gbà yín sílẹ̀!
Le Roi a dit ainsi; qu'Ezéchias ne vous abuse point; car il ne vous pourra pas délivrer.
15 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah rọ̀ yín láti gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nígbà tí ó sọ pé, ‘Olúwa yóò kúkú gbà wá; a kì yóò fi ìlú yìí lé ọba Asiria lọ́wọ́.’
Et qu'Ezéchias ne vous fasse point confier en l'Eternel, en disant; l'Eternel indubitablement nous délivrera; cette ville ne sera point livrée entre les mains du Roi des Assyriens.
16 “Ẹ má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Ohun tí ọba Asiria wí nìyìí. Ẹ fi ẹ̀bùn bá mi rẹ́, kí ẹ sì jáde tọ̀ mí wá. Lẹ́yìn náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò sì jẹ nínú àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mu omi nínú kànga rẹ̀,
N'écoutez point Ezéchias; car ainsi a dit le Roi des Assyriens; faites un accord pour votre bien avec moi, et sortez vers moi, et vous mangerez chacun de sa vigne, et chacun de son figuier, et vous boirez chacun de l'eau de sa citerne;
17 títí tí èmi yóò fi mú un yín lọ sí ilẹ̀ kan tí ó dàbí i tiyín, ilẹ̀ tí ó ní irúgbìn oníhóró àti wáìnì tuntun, ilẹ̀ tí ó ní àkàrà àti ọgbà àjàrà.
Jusqu'à ce que je vienne, et que je vous emmène en un pays qui est comme votre pays, un pays de froment et de bon vin, un pays de pain et de vignes.
18 “Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ṣì yín lọ́nà nígbà tí ó sọ wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá.’ Ǹjẹ́ ọlọ́run orílẹ̀-èdè kan ha ti gbà á kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria bí?
Qu'Ezéchias donc ne vous séduise point, en disant; L'Eternel nous délivrera. Les dieux des nations ont-ils délivré chacun leur pays de la main du Roi des Assyriens?
19 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi ha wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi ha wà? Ǹjẹ́ wọn ti já Samaria gbà kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Où sont les dieux de Hamath et d'Arpad? où sont les dieux de Sépharvajim? et même a-t-on délivré Samarie de ma main?
20 Èwo nínú àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ló ha ti dáàbò bo ilẹ̀ ẹ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa ṣe wá le gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Qui sont ceux d'entre tous les dieux de ces pays-là qui aient délivré leur pays de ma main, [pour dire] que l'Eternel délivrera Jérusalem de ma main?
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà dákẹ́ rọ́rọ́ wọn kò sì mú èsì kankan wá, nítorí ọba ti pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
Mais ils se turent, et ne lui répondirent pas un mot; car le Roi avait commandé, disant; vous ne lui répondrez point.
22 Lẹ́yìn náà ni Eliakimu ọmọ Hilkiah alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé àkọsílẹ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah pẹ̀lú aṣọ wọn ní fífàya, wọ́n sì sọ ohun tí ọ̀gágun ti wí.
Après cela Eliakim fils de Hilkija, Maître d'hôtel et Sebna le Secrétaire, et Joab fils d'Asaph, commis sur les registres, s'en revinrent, les vêtements déchirés, vers Ezéchias, et lui rapportèrent les paroles de Rabsaké.