< Isaiah 36 >

1 Ní ọdún kẹrìnlá ìjọba Hesekiah, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo àwọn ìlú olódi ní ilẹ̀ Juda ó sì kó gbogbo wọn.
La quatorzième année du roi Ézéchias, Sennacherib, roi d'Assyrie, attaqua toutes les villes fortifiées de Juda et les captura.
2 Lẹ́yìn náà, ọba Asiria rán olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Nígbà tí ọ̀gágun náà dúró níbi ojúṣàn adágún ti apá òkè, ní ojú ọ̀nà sí pápá alágbàfọ̀,
Le roi d'Assyrie envoya Rabshakeh de Lakis à Jérusalem auprès du roi Ézéchias avec une grande armée. Il se tenait près de l'aqueduc de l'étang supérieur, sur la route du champ du foulon.
3 Ṣebna Eliakimu ọmọ Hilkiah alábojútó ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé jáde lọ pàdé rẹ̀.
Et Éliakim, fils de Hilkija, qui dirigeait la maison, et Shebna, le scribe, et Joach, fils d'Asaph, le secrétaire, sortirent vers lui.
4 Ọ̀gágun náà sọ fún wọn wí pé, “Ẹ sọ fún Hesekiah, “‘Èyí yìí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ pé: Lórí i kí ni ìwọ gbé ìgbẹ́kẹ̀lé tìrẹ yìí lé?
Rabschaké leur dit: « Dis maintenant à Ézéchias: Le grand roi, le roi d'Assyrie, dit: Quelle est cette confiance en laquelle tu te confies?
5 Ìwọ sọ wí pé ìwọ ní ète àti agbára ogun—ṣùgbọ́n ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ asán. Ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tí ìwọ fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi?
Je dis que vos conseils et votre force pour la guerre ne sont que de vaines paroles. Et maintenant, en qui vous confiez-vous, puisque vous vous êtes révoltés contre moi?
6 Wò ó nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti ẹ̀rún igi ọ̀pá lásán tí í gún ni lọ́wọ́ tí í sì í dọ́gbẹ́ sí ni lára tí a bá gbára lé e! Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti sí àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé e.
Voici, vous vous confiez dans le bâton de ce roseau meurtri, en Égypte, qui, si un homme s'appuie dessus, entre dans sa main et la transperce. Il en est de même de Pharaon, roi d'Égypte, pour tous ceux qui se confient en lui.
7 Bí o bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run wa,” kì í ṣe òun ni Hesekiah ti mú àwọn ibi gíga àti pẹpẹ rẹ̀ kúrò, tí ó sì wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí”?
Mais si vous me dites: « Nous nous confions en Yahvé notre Dieu », n'est-ce pas lui dont Ezéchias a enlevé les hauts lieux et les autels, et qui a dit à Juda et à Jérusalem: « Vous vous prosternerez devant cet autel »?
8 “‘Ẹ wá nísinsin yìí, bá ọ̀gá mi pa ìmọ̀ pọ̀, ọba Asiria, èmi yóò fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin bí ìwọ bá le è fi agẹṣin lé wọn lórí!
Maintenant donc, je te prie de faire un gage à mon maître, le roi d'Assyrie, et je te donnerai deux mille chevaux, si tu es capable de ton côté d'y mettre des cavaliers.
9 Báwo ni ẹ ṣe lè lé ẹyọ kan ṣoṣo padà nínú èyí tí ó kéré jù nínú àwọn balógun olúwa mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti fún kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin?
Comment donc peux-tu détourner le visage d'un seul des moindres serviteurs de mon maître, et te confier à l'Égypte pour les chars et pour les cavaliers?
10 Síwájú sí i, ǹjẹ́ mo wa lè wá bá ilẹ̀ yìí jà kí n sì pa á run láìsí Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ ló sọ pé kí n bá orílẹ̀-èdè yìí jà kí n sì pa á run.’”
Suis-je monté maintenant sans Yahvé contre ce pays pour le détruire? C'est Yahvé qui m'a dit: « Monte contre ce pays, et détruis-le. »"
11 Lẹ́yìn náà ni Eliakimu, Ṣebna àti Joah sọ fún ọ̀gágun náà pé, “Jọ̀wọ́ máa bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀ ní èdè Aramaiki, nítorí pé àwa gbọ́ ọ. Má ṣe bá wa sọ̀rọ̀ ní èdè Heberu ní etí àwọn ènìyàn tí ó wà lórí ògiri mọ́.”
Alors Eliakim, Shebna et Joach dirent à Rabshakeh: « Parle à tes serviteurs en araméen, car nous le comprenons. Ne nous parle pas en langue juive à l'oreille des gens qui sont sur la muraille. »
12 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
Mais Rabschaké dit: « Mon maître m'a-t-il envoyé seulement vers ton maître et vers toi, pour dire ces paroles, et non pas vers les hommes assis sur la muraille, qui mangeront leur propre fumier et boiront leur propre urine avec toi? ».
13 Lẹ́yìn náà ni ọ̀gágun náà dìde tí ó sì ké síta ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
Alors Rabschaké se leva et cria d'une voix forte dans la langue des Juifs, et dit: « Écoutez les paroles du grand roi, le roi d'Assyrie!
14 Ohun tí ọba wí nìyìí, Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn yín jẹ. Òun kò le è gbà yín sílẹ̀!
Le roi dit: « Ne vous laissez pas tromper par Ézéchias, car il ne pourra pas vous délivrer.
15 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah rọ̀ yín láti gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nígbà tí ó sọ pé, ‘Olúwa yóò kúkú gbà wá; a kì yóò fi ìlú yìí lé ọba Asiria lọ́wọ́.’
Qu'Ézéchias ne vous incite pas à avoir confiance en Yahvé, en disant: « Yahvé nous délivrera. Cette ville ne sera pas livrée entre les mains du roi d'Assyrie ».
16 “Ẹ má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Ohun tí ọba Asiria wí nìyìí. Ẹ fi ẹ̀bùn bá mi rẹ́, kí ẹ sì jáde tọ̀ mí wá. Lẹ́yìn náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò sì jẹ nínú àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mu omi nínú kànga rẹ̀,
N'écoutez pas Ézéchias, car le roi d'Assyrie dit: « Faites la paix avec moi et sortez vers moi; et chacun de vous mangera de sa vigne, chacun de son figuier, et chacun de vous boira l'eau de sa citerne;
17 títí tí èmi yóò fi mú un yín lọ sí ilẹ̀ kan tí ó dàbí i tiyín, ilẹ̀ tí ó ní irúgbìn oníhóró àti wáìnì tuntun, ilẹ̀ tí ó ní àkàrà àti ọgbà àjàrà.
jusqu'à ce que je vienne et que je vous emmène dans un pays semblable à votre pays, un pays de blé et de vin nouveau, un pays de pain et de vignes.
18 “Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ṣì yín lọ́nà nígbà tí ó sọ wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá.’ Ǹjẹ́ ọlọ́run orílẹ̀-èdè kan ha ti gbà á kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria bí?
Prenez garde qu'Ézéchias ne vous persuade, en disant: « Yahvé nous délivrera. » Un seul des dieux des nations a-t-il délivré leurs terres de la main du roi d'Assyrie?
19 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi ha wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi ha wà? Ǹjẹ́ wọn ti já Samaria gbà kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Où sont les dieux de Hamath et d'Arpad? Où sont les dieux de Sépharvaïm? Ont-ils délivré Samarie de ma main?
20 Èwo nínú àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ló ha ti dáàbò bo ilẹ̀ ẹ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa ṣe wá le gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Qui sont-ils, parmi tous les dieux de ces pays, ceux qui ont délivré leur pays de ma main, pour que Yahvé délivre Jérusalem de ma main? »
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà dákẹ́ rọ́rọ́ wọn kò sì mú èsì kankan wá, nítorí ọba ti pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
Mais ils gardèrent le silence et ne répondirent rien, car l'ordre du roi était: « Ne lui répondez pas. »
22 Lẹ́yìn náà ni Eliakimu ọmọ Hilkiah alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé àkọsílẹ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah pẹ̀lú aṣọ wọn ní fífàya, wọ́n sì sọ ohun tí ọ̀gágun ti wí.
Alors Éliakim, fils de Hilkija, chef de la maison, et Shebna, le scribe, et Joach, fils d'Asaph, le secrétaire, vinrent auprès d'Ézéchias, les vêtements déchirés, et lui rapportèrent les paroles de Rabschaké.

< Isaiah 36 >