< Isaiah 36 >

1 Ní ọdún kẹrìnlá ìjọba Hesekiah, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo àwọn ìlú olódi ní ilẹ̀ Juda ó sì kó gbogbo wọn.
And it was don in the fourtenthe yeer of kyng Ezechie, Sennacherib, the kyng of Assiriens, stiede on alle the stronge citees of Juda, and took tho.
2 Lẹ́yìn náà, ọba Asiria rán olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Nígbà tí ọ̀gágun náà dúró níbi ojúṣàn adágún ti apá òkè, ní ojú ọ̀nà sí pápá alágbàfọ̀,
And the kyng of Assiriens sente Rapsases fro Lachis to Jerusalem, to kyng Ezechie, with greet power; and he stood at the watir cundit of the hiyere sisterne, in the weie of the feeld of a fullere.
3 Ṣebna Eliakimu ọmọ Hilkiah alábojútó ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé jáde lọ pàdé rẹ̀.
And Eliachym, the sone of Elchie, that was on the hous, yede out to hym, and Sobna, the scryuen, and Joae, the sone of Asaph, the chaunceler.
4 Ọ̀gágun náà sọ fún wọn wí pé, “Ẹ sọ fún Hesekiah, “‘Èyí yìí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ pé: Lórí i kí ni ìwọ gbé ìgbẹ́kẹ̀lé tìrẹ yìí lé?
And Rapsases seide to hem, Seie ye to Ezechie, The greet king, the king of Assiriens, seith these thingis, What is the trist, in which thou tristist?
5 Ìwọ sọ wí pé ìwọ ní ète àti agbára ogun—ṣùgbọ́n ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ asán. Ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tí ìwọ fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi?
ethir bi what councele ether strengthe disposist thou for to rebelle? on whom hast thou trist, for thou hast go awei fro me?
6 Wò ó nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti ẹ̀rún igi ọ̀pá lásán tí í gún ni lọ́wọ́ tí í sì í dọ́gbẹ́ sí ni lára tí a bá gbára lé e! Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti sí àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé e.
Lo! thou tristist on this brokun staf of rehed, on Egipt, on which if a man restith, it schal entre in to his hoond, and schal perse it; so doith Farao, the kyng of Egipt, to alle men that tristen in hym.
7 Bí o bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run wa,” kì í ṣe òun ni Hesekiah ti mú àwọn ibi gíga àti pẹpẹ rẹ̀ kúrò, tí ó sì wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí”?
That if thou answerist to me, We tristen in oure Lord God; whether it is not he, whose hiye places and auteris Esechie dide awei, and he seide to Juda and to Jerusalem, Ye schulen worschipe bifore this auter?
8 “‘Ẹ wá nísinsin yìí, bá ọ̀gá mi pa ìmọ̀ pọ̀, ọba Asiria, èmi yóò fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin bí ìwọ bá le è fi agẹṣin lé wọn lórí!
And now bitake thee to my lord, the kyng of Assiriens, and Y schal yyue to thee twei thousynde of horsis, and thou maist not yyue of thee stieris of tho horsis.
9 Báwo ni ẹ ṣe lè lé ẹyọ kan ṣoṣo padà nínú èyí tí ó kéré jù nínú àwọn balógun olúwa mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti fún kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin?
And hou schalt thou abide the face of the iuge of o place of the lesse seruauntis of my lord? That if thou tristist in Egipt, and in cartis, and in knyytis;
10 Síwájú sí i, ǹjẹ́ mo wa lè wá bá ilẹ̀ yìí jà kí n sì pa á run láìsí Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ ló sọ pé kí n bá orílẹ̀-èdè yìí jà kí n sì pa á run.’”
and now whethir Y stiede to this lond with out the Lord, that Y schulde distrie it? The Lord seide to me, Stie thou on this lond, and distrie thou it.
11 Lẹ́yìn náà ni Eliakimu, Ṣebna àti Joah sọ fún ọ̀gágun náà pé, “Jọ̀wọ́ máa bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀ ní èdè Aramaiki, nítorí pé àwa gbọ́ ọ. Má ṣe bá wa sọ̀rọ̀ ní èdè Heberu ní etí àwọn ènìyàn tí ó wà lórí ògiri mọ́.”
And Eliachym, and Sobna, and Joae, seiden to Rapsaces, Speke thou to thi seruauntis bi the langage of Sirie, for we vndurstonden; speke thou not to vs bi the langage of Jewis in the eeris of the puple, which is on the wal.
12 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
And Rapsaces seide to hem, Whether mi lord sente me to thi lord, and to thee, that Y schulde speke alle these wordis, and not rathere to the men that sitten on the wal, that thei ete her toordis, and drynke the pisse of her feet with you?
13 Lẹ́yìn náà ni ọ̀gágun náà dìde tí ó sì ké síta ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
And Rapsaces stood, and criede with greet vois in the langage of Jewis, and seide, Here ye the wordis of the greet kyng, the kyng of Assiriens.
14 Ohun tí ọba wí nìyìí, Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn yín jẹ. Òun kò le è gbà yín sílẹ̀!
The kyng seith these thingis, Esechie disseyue not you, for he may not delyuere you;
15 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah rọ̀ yín láti gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nígbà tí ó sọ pé, ‘Olúwa yóò kúkú gbà wá; a kì yóò fi ìlú yìí lé ọba Asiria lọ́wọ́.’
and Ezechie yyue not to you trist on the Lord, and seie, The Lord delyuerynge schal delyuere vs; this citee schal not be youun in to the hoond of the kyng of Assiriens.
16 “Ẹ má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Ohun tí ọba Asiria wí nìyìí. Ẹ fi ẹ̀bùn bá mi rẹ́, kí ẹ sì jáde tọ̀ mí wá. Lẹ́yìn náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò sì jẹ nínú àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mu omi nínú kànga rẹ̀,
Nyle ye here Ezechie. For whi the kyng of Assiriens seith these thingis, Make ye blessyng with me, and go ye out to me; and ete ye ech man his vyner, and ech man his fige tre, and drynke ye ech man the water of his cisterne,
17 títí tí èmi yóò fi mú un yín lọ sí ilẹ̀ kan tí ó dàbí i tiyín, ilẹ̀ tí ó ní irúgbìn oníhóró àti wáìnì tuntun, ilẹ̀ tí ó ní àkàrà àti ọgbà àjàrà.
til Y come, and take awei you to a lond which is as youre lond; to a lond of whete and of wyn, to a lond of looues and of vyneris.
18 “Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ṣì yín lọ́nà nígbà tí ó sọ wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá.’ Ǹjẹ́ ọlọ́run orílẹ̀-èdè kan ha ti gbà á kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria bí?
Ezechie disturble not you, and seie, The Lord schal delyuere vs. Whether the goddis of folkis delyuereden ech his lond fro the hond of the kyng of Assiriens?
19 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi ha wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi ha wà? Ǹjẹ́ wọn ti já Samaria gbà kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Where is the god of Emath, and of Arphat? Where is the god of Sepharuaym? Whethir thei delyueriden Samarie fro myn hond?
20 Èwo nínú àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ló ha ti dáàbò bo ilẹ̀ ẹ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa ṣe wá le gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Who is of alle goddis of these londis, that delyueride his lond fro myn hond, that the Lord delyuere Jerusalem fro myn hond?
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà dákẹ́ rọ́rọ́ wọn kò sì mú èsì kankan wá, nítorí ọba ti pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
And thei weren stille, and answeriden not to hym a word. For whi the kyng comaundide to hem, and seide, Answere ye not to him.
22 Lẹ́yìn náà ni Eliakimu ọmọ Hilkiah alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé àkọsílẹ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah pẹ̀lú aṣọ wọn ní fífàya, wọ́n sì sọ ohun tí ọ̀gágun ti wí.
And Eliachym, the sone of Elchie, that was on the hous, and Sobna, the scryueyn, and Joae, the sone of Asaph, chaunceler, entriden with to-rent clothis to Ezechie, and telde to hym the wordis of Rapsaces.

< Isaiah 36 >