< Isaiah 35 >
1 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
Freuen wird sich Wüste und Dürre, und frohlocken die Einöde, und blühen wie die Rose.
2 ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
Blühend erblüht sie und frohlockt; nur Frohlocken und Jubel ist da. Die Herrlichkeit des Libanon wird ihr gegeben, Karmels und Scharons Ehre. Sie sehen die Herrlichkeit Jehovahs, die Ehre unseres Gottes.
3 Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
Stärket die schlaffen Hände und kräftigt die strauchelnden Knie.
4 Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
Sprecht zu den übereiligen Herzen: Seid stark, fürchtet euch nicht! Siehe, euer Gott kommt zur Rache, zur Vergeltung Gottes; Er kommt und rettet euch.
5 Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
Dann werden aufgetan der Blinden Augen und die Ohren der Tauben geöffnet.
6 Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
Dann hüpft wie ein Hirsch der Lahme und des Stummen Zunge jubelt, denn Wasser brechen in der Wüste hervor und Bäche in der Einöde.
7 Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
Zum Teiche wird die Sandwüste und das durstige Land zum Quellengrunde der Wasser. In der Drachen Wohnort, wo er lagert, ist Gras statt Rohr und Binsen.
8 Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
Und eine Bahn wird dort sein und ein Weg, und man nennt ihn den Weg der Heiligkeit. Kein Unreiner geht darüber, sondern er ist für sie. Wer auf dem Wege geht, auch Narren, gehen nicht irre.
9 Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
Dort ist kein Löwe und kein reißend Tier geht darin hinauf; es läßt sich dort nicht finden. Aber die Erlösten gehen ihn.
10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Und die Losgekauften Jehovahs kehren zurück und kommen mit Jubeln nach Zion, und ewige Fröhlichkeit auf ihrem Haupt; Freude und Fröhlichkeit ergreift sie, und Gram flieht und Seufzer.