< Isaiah 35 >

1 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
Elle se réjouira, la terre déserte et sans chemin, et elle exultera, la solitude, et fleurira comme le lis.
2 ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
Germant, elle germera, et elle exultera toute joyeuse et chantant des louanges; la gloire du Liban lui a été donnée, la beauté du Carmel et du Saron; eux-mêmes verront la gloire du Seigneur, et la majesté de notre Dieu.
3 Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
Fortifiez les mains languissantes, et affermissez les genoux débiles.
4 Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
Dites aux pusillanimes: Prenez courage, et ne craignez point; car voici que votre Dieu amènera la vengeance de rétribution; Dieu lui-même viendra, et il vous sauvera.
5 Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
Alors les yeux des aveugles s’ouvriront, et les oreilles des sourds entendront.
6 Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
Alors le boiteux bondira comme le cerf, et la langue des muets sera déliée; parce que des eaux se sont répandues dans le désert, et des torrents dans la solitude.
7 Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
Et la terre qui était aride sera comme un étang, et celle qui avait soif, comme des fontaines d’eaux. Dans les repaires dans lesquels auparavant habitaient des dragons, croîtra la verdure du roseau et du jonc.
8 Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
Et là sera un sentier et une voie, et elle sera appelée la voie sainte; l’impur n’y passera pas, et ce sera pour vous une voie droite, en sorte que les ignorants ne s’y égareront pas.
9 Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
Il n’y aura pas là de bon, et une mauvaise bête n’y montera pas, et ne s’y trouvera pas; mais ils y marcheront, ceux qui auront été délivrés.
10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Et les rachetés par le Seigneur retourneront et viendront à Si on avec des chants de louange; et une allégresse éternelle sera sur leur tête; ils obtiendront la joie et l’allégresse, et la douleur fuira ainsi que le gémissement.

< Isaiah 35 >