< Isaiah 35 >
1 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
Le désert et la terre aride sont dans la joie, et la steppe dans l'allégresse, et elle fleurit comme le narcisse,
2 ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
elle se couvre de fleurs et se réjouit heureuse et triomphante; la gloire du Liban lui est donnée, la magnificence du Carmel et de Saron; ils voient la gloire de l'Éternel, la magnificence de notre Dieu.
3 Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
Fortifiez les mains lâches, et affermissez les genoux chancelants!
4 Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
Dites aux cœurs alarmés: « Courage! soyez sans peur! voici votre Dieu, la vengeance approche, représaille de Dieu; Il vient et vous sauvera. »
5 Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
Alors s'ouvriront les yeux des aveugles, et les oreilles des sourds seront ouvertes;
6 Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
alors comme un cerf le perclus bondira, et la langue du muet chantera, car les eaux jaillissent dans le désert et des ruisseaux dans la plaine aride.
7 Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
Le mirage des sables devient un vrai lac, et la terre desséchée des sources d'eaux: dans le gîte des chacals où est leur repaire, sera un parc pour le jonc et le roseau.
8 Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
Et il y aura une route et une chaussée, et elle s'appellera la Voie sainte; nul impur n'y passera; elle sera pour eux seuls; qui suivra cette route, même un insensé, ne pourra s'égarer.
9 Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
Là point de lion; nulle bête féroce n'y mettra le pied; il ne s'y en trouvera point; les délivrés y marcheront.
10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Et les rachetés de l'Éternel reviendront et s'avanceront vers Sion avec chant de triomphe, et une joie éternelle couronnant leur tête: le bonheur et la joie viendront au-devant d'eux, et le chagrin et les soupirs fuiront.