< Isaiah 35 >
1 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
Réjouis-toi, désert altéré; que le désert tressaille d'allégresse, qu'il se couvre de fleurs comme le lis.
2 ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
Et les déserts du Jourdain fleuriront, et ils seront dans la joie: la gloire du Liban leur a été donnée, et les honneurs du Carmel; et mon peuple verra la gloire du Seigneur et la grandeur de Dieu.
3 Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
Fortifiez-vous, mains affaiblies, genoux tremblants.
4 Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
Consolez-vous l'un l'autre, cœurs défaillants; prenez courage, n'ayez pas peur; voici notre Dieu, il vous rend et il vous rendra justice; il viendra lui-même, et il nous sauvera.
5 Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
Alors s'ouvriront les yeux des aveugles, et les oreilles des sourds ouïront.
6 Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
Alors le boiteux sautera comme un cerf; la langue nouée parlera facilement, parce que l'onde aura jailli dans le désert, et un torrent sur une terre altérée.
7 Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
Et les champs arides seront changés en nappes d'eau, et il y aura des fontaines sur une terre altérée; là seront la joie des oiseaux, le séjour du roseau et des étangs.
8 Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
Là il y aura une voie pure, qu'on nommera la voie sainte, et jamais être impur n'y passera; et il n'y aura point de voie impure, mais les dispersés y marcheront et ne s'égareront pas.
9 Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
Il n'y aura pas de lion; nulle bête farouche n'y viendra ou n'y sera trouvée; mais là marcheront les hommes rachetés
10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Et rassemblés par le Seigneur; là sera leur refuge, et ils rentreront à Sion, transportés d'allégresse; et une joie perpétuelle couronnera leurs têtes; on verra sur leur front la louange et le ravissement; la joie aura pris possession d'eux; la douleur, la tristesse, les gémissements se seront enfuis.