< Isaiah 35 >

1 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
[Some day, it will be as though] the desert [and other very] dry areas are glad [DOU]; the desert will rejoice and flowers will blossom. Like crocuses/daffodils,
2 ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
the desert will produce flowers abundantly; [it will be as though] everything is rejoicing and singing! The deserts will become as beautiful as [SIM] [the trees in] Lebanon, as fertile [SIM] as the plains of the Sharon and Carmel [areas]. [There] people will see the glory of Yahweh; they will see that he is magnificent.
3 Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
[So], encourage those who are tired and weak.
4 Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
Say to those who are afraid, “Be strong and do not be afraid, because our God is going to come to get revenge [on his enemies]; he will (pay them back/punish them) for what they have done, and he will rescue you.”
5 Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
When he does that, [he will enable] blind people to see and [enable] deaf people to hear.
6 Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
Lame people will leap like deer, and those who have been unable to speak will sing joyfully. Water will gush out [from springs] in the desert; streams will flow in the desert.
7 Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
The very dry ground will become a pool of water, and springs will provide water for the dry land. Grass and reeds and papyrus will grow in places where the jackals/wolves lived previously.
8 Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
And there will be a highway through that land; it will be called ‘the Holy Highway’. People who are not acceptable to God will not walk on that road; it will be only for those who conduct their lives as God wants them to; foolish people will become lost while walking on that road.
9 Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
There will not be any lions there or any other dangerous animals along that road. Only those who have been freed [from being slaves in Babylonia] will walk on it.
10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Those whom Yahweh has freed will return to Jerusalem; they will sing as they enter the city; they will be extremely joyful [MET, PRS] forever. No longer will they be sad or mourn; they will be [completely] joyful [DOU].

< Isaiah 35 >