< Isaiah 34 >
1 Súnmọ́ tòsí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti gbọ́, tẹ́tí sílẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn jẹ́ kí ayé gbọ́, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti ohun gbogbo tí ó ti inú rẹ̀ jáde.
¡Acérquense, naciones, para escuchar! Escuchad, pueblos. Que oiga la tierra y todo lo que contiene, el mundo, y todo lo que proviene de él.
2 Nítorí ìbínú Olúwa ń bẹ lára gbogbo orílẹ̀-èdè, àti ìrunú rẹ̀ lórí gbogbo ogun wọn: o ti fi wọ́n fún pípa.
Porque Yahvé está enfurecido contra todas las naciones, y enojado con todos sus ejércitos. Los ha destruido por completo. Los ha entregado a la matanza.
3 Àwọn ti a pa nínú wọn ni a ó sì jù sóde, òórùn wọn yóò ti inú òkú wọn jáde, àwọn òkè ńlá yóò sì yọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ wọn.
Sus muertos también serán expulsados, y subirá el hedor de sus cadáveres. Las montañas se derretirán en su sangre.
4 Gbogbo àwọn ogun ọ̀run ni yóò di yíyọ́, a ó sì ká àwọn ọ̀run jọ bí i tákàdá, gbogbo ogun wọn yóò si ṣubú lulẹ̀, bí ewé ti n bọ́ kúrò lára àjàrà, àti bí i bíbọ́ èso lára igi ọ̀pọ̀tọ́.
Todo el ejército del cielo será disuelto. El cielo se enrollará como un pergamino, y todos sus ejércitos se desvanecerán, como se desvanece una hoja de una vid o de una higuera.
5 Nítorí ti a rẹ idà mi ní ọ̀run, kíyèsi í, yóò sọ̀kalẹ̀ wá sórí Edomu, sórí àwọn ènìyàn tí mo ti parun fún ìdájọ́.
Porque mi espada ha bebido hasta la saciedad en el cielo. He aquí que descenderá sobre Edom, y sobre el pueblo de mi maldición, para el juicio.
6 Idà Olúwa kún fún ẹ̀jẹ̀ a mú un sanra fún ọ̀rá, àti fún ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, fún ọ̀rá ìwé àgbò— nítorí Olúwa ni ìrúbọ kan ní Bosra, àti ìpakúpa ńlá kan ní ilẹ̀ Edomu.
La espada de Yahvé está llena de sangre. Está cubierto de grasa, de sangre de corderos y cabras, con la grasa de los riñones de los carneros; porque Yahvé tiene un sacrificio en Bozra, y una gran matanza en la tierra de Edom.
7 Àti àwọn àgbáǹréré yóò ba wọn sọ̀kalẹ̀ wá, àti àwọn ẹgbọrọ màlúù pẹ̀lú àwọn akọ màlúù, ilé wọn ni a ó fi ẹ̀jẹ̀ rin, a ó sì fi ọ̀rá sọ ekuru wọn di ọlọ́ràá.
Los bueyes salvajes bajarán con ellos, y los novillos con los toros poderosos; y su tierra se embriagará de sangre, y su polvo engrasado con grasa.
8 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san Olúwa ni, àti ọdún ìsanpadà, nítorí ọ̀ràn Sioni.
Porque Yahvé tiene un día de venganza, un año de recompensa para la causa de Sion.
9 Odò rẹ̀ ni a ó sì sọ di ọ̀dà, àti eruku rẹ̀ di imí-ọjọ́, ilẹ̀ rẹ̀ yóò sì di ọ̀dà tí ń jóná.
Sus arroyos se convertirán en brea, su polvo en azufre, y su tierra se convertirá en brea ardiente.
10 A kì yóò pa á ní òru tàbí ní ọ̀sán; èéfín rẹ̀ yóò gòkè láéláé: yóò dahoro láti ìran dé ìran, kò sí ẹnìkan tí yóò là á kọjá láé àti láéláé.
No se apagará ni de noche ni de día. Su humo subirá para siempre. De generación en generación, será un residuo. Nadie pasará por ella para siempre.
11 Òwìwí aginjù, àti àkàlà ni yóò ni ín, àti òwìwí àti ẹyẹ ìwò ni yóò máa gbé inú rẹ̀. Ọlọ́run yóò sì na sórí Edomu okùn ìwọ̀n ìparun àti òkúta òfo.
Pero el pelícano y el puercoespín la poseerán. El búho y el cuervo habitarán en él. Él estirará la línea de confusión sobre ella, y la plomada del vacío.
12 Ní ti àwọn ìjòyè rẹ̀ ẹnìkan kì yóò sí níbẹ̀ tiwọn ó pè wá sí ìjọba, gbogbo àwọn olórí i rẹ̀ yóò sì di asán.
Llamarán a sus nobles al reino, pero ninguno estará allí; y todos sus príncipes no serán nada.
13 Ẹ̀gún yóò sì hù jáde nínú àwọn ààfin rẹ̀ wọ̀nyí, ẹ̀gún ọ̀gán nínú ìlú olódi rẹ̀. Yóò jẹ́ ibùgbé àwọn akátá àti àgbàlá fún àwọn òwìwí.
En sus palacios surgirán espinas, ortigas y cardos en sus fortalezas; y será morada de chacales, un tribunal para avestruces.
14 Àwọn ẹranko ijù àti àwọn ìkookò ni yóò pàdé, àti ewúrẹ́ igbó kan yóò máa kọ sí èkejì rẹ̀, iwin yóò máa gbé ibẹ̀ pẹ̀lú, yóò sì rí ibi ìsinmi fún ara rẹ̀.
Los animales salvajes del desierto se encontrarán con los lobos, y la cabra salvaje gritará a su compañero. Sí, la criatura nocturna se instalará allí, y encontrará un lugar de descanso.
15 Òwìwí yóò tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ síbẹ̀, yóò yé, yóò sì pa, yóò sì kójọ lábẹ́ òjìji rẹ̀: àwọn gúnnugún yóò péjọ síbẹ̀ pẹ̀lú, olúkúlùkù pẹ̀lú ẹnìkejì rẹ̀.
La serpiente flecha hará su nido allí, y se acuestan, empollan y reúnen bajo su sombra. Sí, los cometas se reunirán allí, cada uno con su pareja.
16 Ẹ wo ìwé Olúwa, kí ẹ sì kà. Ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí kì yóò yẹ̀, kò sí ọ̀kan tí yóò fẹ́ èkejì rẹ̀ kù: nítorí Olúwa ti pàṣẹ ẹnu rẹ̀ ló sì fi kó wọn jọ Ẹ̀mí rẹ̀ ló sì fi tò wọ́n jọ.
Busca en el libro de Yahvé y lee: no faltará ninguno de ellos. A ninguna le faltará su pareja. Porque mi boca lo ha ordenado, y su Espíritu los ha reunido.
17 Ó ti di ìbò fún wọn, ọwọ́ rẹ̀ sì ti pín in fún wọn nípa títa okùn, wọn ó jogún rẹ̀ láéláé, láti ìran dé ìran ni wọn ó máa gbé inú rẹ̀.
Ha echado la suerte por ellos, y su mano se la ha repartido con una línea de medida. La poseerán para siempre. De generación en generación, habitarán en ella.