< Isaiah 33 >

1 Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun, ìwọ tí a kò tí ì parun! Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀, ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́! Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run; a ó pa ìwọ náà run, nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani, a ó da ìwọ náà.
Ve dig, du fördärvare, som själv har gått fri ifrån fördärvet! Ve dig, du härjare, som själv har undgått förhärjning! När du har fyllt ditt mått att fördärva, drabbas du själv av fördärvet; när du har fullbordat till härjande drabbas du själv av förhärjning.
2 Olúwa ṣàánú fún wa àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ. Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀ ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
HERRE, var oss nådig, dig förbida vi. Var dessas arm var morgon; ja, var vår frälsning i nödens tid.
3 Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá, nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
För ditt väldiga dån fly folken bort; när du reser dig upp, förskingras folkslagen.
4 Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú; gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.
Och man får skövla och taga byte efter eder, såsom gräsmaskar skövla; såsom gräshoppor störta fram, så störtar man över det.
5 A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga, Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
HERREN är hög, ty han bor i höjden; han uppfyller Sion med rätt och rättfärdighet.
6 Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀; ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.
Ja, trygga tider skola komma för dig! Vishet och kunskap bereda Sion frälsning i rikt mått, och HERRENS fruktan skall vara deras skatt.
7 Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré ẹkún ní òpópónà; àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
Hör, deras hjältar klaga därute, fredsbudbärarna gråta bitterligen.
8 Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì, kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà. A ti ba àdéhùn jẹ́, a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí, a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
Vägarna äro öde, ingen går mer på stigarna. Han bryter förbund, han aktar städer ringa, människor räknar han för intet.
9 Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù, ojú ti Lebanoni ó sì sá Ṣaroni sì dàbí aginjù, àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.
Landet ligger sörjande och försmäktar, Libanon blyges och står förvissnat, Saron har blivit likt en hedmark, Basans och Karmels skogar fälla sina löv.
10 “Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí. “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga, ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
Men nu vill jag stå upp, säger HERREN, nu vill jag resa mig upp, nu vill jag upphäva mig.
11 Ìwọ lóyún ìyàngbò, o sì bí koríko; èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
Med halm gån I havande, och strå föden I; edert raseri är en eld, som skall förtära eder själva.
12 A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú; bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”
Folken skola förbrännas och bliva till aska, ja, likna avhugget törne, som brinner upp i eld.
13 Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun tí mo ti ṣe; ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
Så hören nu, I som fjärran ärer, vad jag har gjort; förnimmen min makt, I som nära ären.
14 Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni; ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́: “Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun? Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
Syndarna i Sion bliva förskräckta, bävan griper de gudlösa. »Vem av oss kan härda ut vid en förtärande eld, vem av oss kan bo vid en evig glöd?»
15 Ẹni tí ó ń rìn lódodo tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́, tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi,
Den som vandrar i rättfärdighet och talar, vad rätt är, den som föraktar, vad som vinnes genom orätt och våld, och den som avhåller sina händer från att taga mutor, den som tillstoppar sina öron för att icke höra om blodsgärningar och tillsluter sina ögon för att icke se, vad ont är,
16 Òun náà yóò gbé ní ibi gíga, ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi. A ó mú oúnjẹ fún un, omi rẹ̀ yóò sì dájú.
han skall bo på höjderna, klippfästen skola vara hans värn, sitt bröd skall han få, och vatten skall han hava beständigt.
17 Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀ yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
Ja, dina ögon skola skåda en konung i hans härlighet, de skola blicka ut över ett vidsträckt land.
18 Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá: “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà? Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
Då skall ditt hjärta tänka tillbaka på förskräckelsens tid: »Var är nu skatteräknaren, var är nu skattevägaren, var är den som räknade tornen?»
19 Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́, àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin, pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.
Du slipper då att se det fräcka folket, folket, vars obegripliga språk man ej kunde förstå, vars stammande tungomål ingen kunde tyda.
20 Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa, ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu, ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà; àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
Men skåda på Sion, våra högtiders stad, låt dina ögon betrakta Jerusalem: det är en säker boning, ett tält, som icke flyttas bort, ett vars pluggar aldrig ryckas upp och av vars streck intet enda brister sönder.
21 Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ alágbára kan fún wa. Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńlá ńlá àti odò kéékèèké. Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn, ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
Ja, vi hava där HERREN, den väldige; han är för oss såsom floder och breda strömmar; ingen roddflotta kommer där fram, och det väldigaste skepp kan ej fara däröver.
22 Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa òun ni ọba wa; òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.
Ty HERREN är vår domare, HERREN är vår härskare, HERREN är vår konung, han frälsar oss.
23 Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀: Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀, wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn, lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
Dina tåg hänga slappa, de hålla ej masten stadig, ej seglet spänt. Men då skall rövat gods utskiftas i myckenhet, ja, också de lama skola då taga byte.
24 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,” a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.
Och ingen av invånarna skall säga: »Jag är svag», ty folket, som där bor, har fått sin missgärning förlåten.

< Isaiah 33 >