< Isaiah 33 >

1 Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun, ìwọ tí a kò tí ì parun! Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀, ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́! Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run; a ó pa ìwọ náà run, nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani, a ó da ìwọ náà.
وای بر شما ای آشوری‌ها که همه را غارت می‌کنید و پیمانهایی را که با قومهای دیگر بسته‌اید زیر پا می‌گذارید. به‌زودی این غارت و خیانت شما پایان خواهد یافت و آنگاه خود شما مورد غارت و خیانت واقع خواهید شد.
2 Olúwa ṣàánú fún wa àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ. Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀ ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
ای خداوند، بر ما رحم کن، زیرا چشم امید ما به توست. هر بامداد به ما قدرت عطا کن و ما را از سختی نجات ده.
3 Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá, nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
دشمن وقتی صدایت را بشنود خواهد گریخت؛ زمانی که تو برخیزی قومها پراکنده خواهند شد.
4 Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú; gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.
اموال دشمنان ما، مانند مزرعه‌ای که مورد هجوم ملخ واقع شده باشد، غارت خواهد گردید.
5 A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga, Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
خداوند بزرگ و والاست و بر همه چیز تسلط دارد. او اورشلیم را از عدل و انصاف پر خواهد ساخت
6 Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀; ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.
و به قوم یهودا استحکام خواهد بخشید. او همیشه از قوم خود حمایت می‌کند و به ایشان حکمت و بصیرت می‌بخشد. خداترسی گنج بزرگ ایشان است!
7 Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré ẹkún ní òpópónà; àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
اما در حال حاضر فرستادگان قوم یهودا از شدت ناامیدی گریانند، زیرا آشور تقاضای ایشان را برای صلح نپذیرفته است.
8 Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì, kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà. A ti ba àdéhùn jẹ́, a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí, a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
شاهراههای یهودا خراب شده و دیگر اثری از مسافران نیست. آشوری‌ها پیمان صلح را زیر پا نهاده‌اند و به وعده‌هایی که در حضور گواهان داده‌اند توجهی ندارند؛ آنها به هیچ‌کس اعتنا نمی‌کنند.
9 Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù, ojú ti Lebanoni ó sì sá Ṣaroni sì dàbí aginjù, àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.
سرزمین اسرائیل از بین رفته، لبنان نابود شده، شارون به بیابان تبدیل گشته و برگهای درختان باشان و کرمل ریخته است.
10 “Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí. “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga, ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
اما خداوند می‌فرماید: «برمی‌خیزم و قدرت و توانایی خود را نشان می‌دهم!
11 Ìwọ lóyún ìyàngbò, o sì bí koríko; èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
ای آشوری‌ها، هر چه تلاش کنید سودی نخواهد داشت. نفس خودتان به آتش تبدیل شده، شما را خواهد کشت.
12 A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú; bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”
سپاهیان شما مثل خارهایی که در آتش انداخته می‌شوند، سوخته و خاکستر خواهند شد.
13 Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun tí mo ti ṣe; ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
ای قومهایی که دور هستید، به آنچه کرده‌ام توجه کنید؛ و ای قومهایی که نزدیک هستید، به قدرت من پی ببرید.»
14 Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni; ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́: “Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun? Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
گناهکاران و خدانشناسانی که در اورشلیم هستند از ترس می‌لرزند و فریاد برمی‌آورند: «کدام یک از ما می‌تواند از آتش سوزان و دائمی مجازات خدا جان به در برد؟»
15 Ẹni tí ó ń rìn lódodo tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́, tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi,
کسی می‌تواند از این آتش جان به در برد که درستکار باشد و به راستی عمل نماید، به خاطر منافع خود ظلم نکند، رشوه نگیرد، و با کسانی که شرارت و جنایت می‌کنند همدست نشود.
16 Òun náà yóò gbé ní ibi gíga, ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi. A ó mú oúnjẹ fún un, omi rẹ̀ yóò sì dájú.
چنین اشخاص در امنیت به سر خواهند برد و صخره‌های مستحکم، پناهگاه ایشان خواهند بود.
17 Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀ yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
بار دیگر چشمان شما پادشاهتان را در شکوه و زیبایی‌اش خواهند دید و سرزمین وسیعی را که او بر آن سلطنت می‌کند مشاهده خواهند کرد.
18 Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá: “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà? Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
در آن زمان به روزهای ترسناکی که در گذشته داشتید فکر خواهید کرد روزهایی که سرداران آشور برجهای شما را می‌شمردند تا ببینند چقدر غنیمت می‌توانند از شما به دست آورند.
19 Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́, àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin, pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.
ولی آن روزها گذشته است و از آن قوم ستمگری که زبانشان را نمی‌فهمیدید دیگر اثری نیست.
20 Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa, ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu, ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà; àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
به اورشلیم، این شهر جشنهای مقدّس نگاه کنید و ببینید چگونه در صلح و امنیت به سر می‌برد! اورشلیم محکم و پا برجا خواهد بود درست مانند خیمه‌ای که میخهایش کنده نمی‌شود و طنابهایش پاره نمی‌گردد.
21 Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ alágbára kan fún wa. Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńlá ńlá àti odò kéékèèké. Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn, ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
خداوند پرجلال ما را همچون رودخانه‌ای وسیع محافظت خواهد کرد تا هیچ دشمنی نتواند از آن عبور کرده، به ما یورش برد!
22 Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa òun ni ọba wa; òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.
خداوند پادشاه و رهبر ماست؛ او از ما مراقبت خواهد کرد و ما را نجات خواهد داد.
23 Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀: Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀, wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn, lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
طناب کشتی‌های دشمن سست خواهد شد و پایه‌های دکل را نگه نخواهد داشت و افراد دشمن نخواهند توانست بادبانها را بکشند. ما تمام غنایم دشمن را به چنگ خواهیم آورد؛ حتی لنگان نیز سهمی از این غنایم خواهند برد.
24 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,” a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.
هر که در سرزمین ما باشد دیگر نخواهد گفت: «بیمار هستم»؛ و تمام گناهان ساکنان این سرزمین بخشیده خواهد شد.

< Isaiah 33 >