< Isaiah 33 >

1 Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun, ìwọ tí a kò tí ì parun! Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀, ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́! Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run; a ó pa ìwọ náà run, nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani, a ó da ìwọ náà.
Oh pusztító, de téged nem pusztítottak, hűtlenkedő, de ellened nem hűtlenkedtek! Amint végeztél a pusztítással, téged fognak pusztítani; amint befejezted a hűtlenkedést, ellened fognak hűtlenkedni.
2 Olúwa ṣàánú fún wa àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ. Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀ ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
Örökkévaló, könyörülj rajtunk, hozzád reménykedtünk; légy a karjuk reggelenként, segítségünk is a szorongatás idejében.
3 Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá, nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
A zajongás hangjától elbujdostak népek; felemelkedésedtől elszóródtak nemzetek.
4 Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú; gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.
És összeszedik zsákmányotokat, amint összeszedik a sáskát, amint futkos a szöcske, úgy futkosnak rajta.
5 A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga, Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
Magasztos az Örökkévaló, mert magasban lakozik, megtöltötte Cziónt joggal és igazsággal.
6 Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀; ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.
És meglesz időd biztossága, üdvnek gazdagsága, bölcsesség és megismerés; az istenfélelem az az ő kincse.
7 Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré ẹkún ní òpópónà; àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
Íme hőseik kiáltanak kinn, a béke követei keservesen sírnak.
8 Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì, kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà. A ti ba àdéhùn jẹ́, a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí, a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
Elpusztultak az országutak, megszűnt az útonjáró; fölbontott szövetséget, megvetett városokat, nem vett semmibe embert.
9 Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù, ojú ti Lebanoni ó sì sá Ṣaroni sì dàbí aginjù, àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.
Gyászol, elhervadt a föld, megszégyenül a Libanon, elfonnyadt; olyan lett a Sárón mint a sivatag, lombját leveti Básán és Kármell.
10 “Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí. “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga, ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
Most felkelek, mondja az Örökkévaló, most fölmagasodom, most felemelkedem.
11 Ìwọ lóyún ìyàngbò, o sì bí koríko; èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
Fogantok pozdorját, szültök tarlót, leheletetek tűz, mely megemészt benneteket.
12 A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú; bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”
És lesznek a népek mészkemencék, levágott tövisek, tűzzel gyújtatnak meg.
13 Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun tí mo ti ṣe; ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
Halljátok távollevők, mit cselekedtem és tudjátok meg közelvalók hatalmamat.
14 Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni; ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́: “Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun? Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
Remegtek Cziónban a vétkesek, reszketés fogta el az istenteleneket ki lakhatik közülünk emésztő tűznél, ki lakhatik az örök lángoknál?
15 Ẹni tí ó ń rìn lódodo tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́, tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi,
Aki igazságban jár és egyenességet beszél, megveti a zsarolt nyereséget, megrázza kezét, hogy ne fogjon vesztegetést, betömi fülét, hogy ne halljon vérbűnt és behunyja szemeit, hogy ne lásson rosszat:
16 Òun náà yóò gbé ní ibi gíga, ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi. A ó mú oúnjẹ fún un, omi rẹ̀ yóò sì dájú.
az magasban fog lakozni, sziklák várai az ő menedéke: kenyere megadatik, vize maradandó.
17 Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀ yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
Királyt az ő szépségében nézik majd szemeid, látni fognak tágas országot.
18 Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá: “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà? Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
Szíved félelemmel gondolja: hol az író, hol a mérlegelő, hol aki összeírja a tornyokat?
19 Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́, àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin, pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.
A durva népet nem látod, a homályos ajkú népet, mely meg nem érthető, a dadogó értelem nélküli nyelvűt.
20 Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa, ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu, ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà; àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
Nézd Cziónt, gyülekezésünk városát, szemeid látni fogják Jeruzsálemet gondtalan hajléknak, sátornak, mely nem mozdul, melynek szögeit soha nem szakítják ki, melynek kötelei nem szakadnak szét, egy sem.
21 Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ alágbára kan fún wa. Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńlá ńlá àti odò kéékèèké. Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn, ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
Hanem hatalmas ott számunkra az Örökkévaló, folyók, széles partú folyamok helyett, rajta nem jár evezős hajóraj, és hatalmas hajó nem kel át rajta.
22 Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa òun ni ọba wa; òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.
Mert az Örökkévaló a bíránk, az Örökkévaló a törvényadónk, az Örökkévaló a királyunk, ő megsegít bennünket.
23 Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀: Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀, wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn, lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
Meglazultak köteleid, nem tartják erősen árbócfájuk talapját, nem feszítik ki a vitorlát; akkor osztottak zsákmányos ragadmányt sokat, sánták prédáltak prédát,
24 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,” a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.
és nem mondja lakos: beteg vagyok – a nép, mely benne lakik, ment a bűntől.

< Isaiah 33 >