< Isaiah 32 >
1 Wò ó, ọba kan yóò jẹ nínú òdodo àwọn olórí yóò máa fi ìdájọ́ ṣe àkóso.
Voici qu’un roi régnera selon la justice, et les princes gouverneront avec droiture.
2 Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò jẹ́ bí ibi ìṣápamọ́ kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ àti ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì, gẹ́gẹ́ bí odò omi ní ilẹ̀ aṣálẹ̀, àti bí òjìji àpáta ńlá ní ilẹ̀ gbígbẹ.
Et chacun d’eux sera un abri contre le vent et un refuge contre la tempête, comme des courants d’eau dans une terre aride, comme l’ombre d’un grand rocher dans un pays désolé.
3 Nígbà náà ni ojú àwọn tí ó rí kò ní padé mọ́, àti etí àwọn tí ó gbọ́ yóò tẹ́tí sílẹ̀.
Les yeux de ceux qui voient ne seront plus aveuglés, et les oreilles de ceux qui entendent seront attentives.
4 Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè, àti ahọ́n tí ń kólòlò ni yóò là geerege.
Le cœur des hommes légers sera habile à comprendre, et la langue des bègues adroite à parler nettement.
5 A kò ní pe òmùgọ̀ ní ọlọ́lá mọ́ tàbí kí a fi ọ̀wọ̀ tí ó ga jù fún aláìlóòótọ́ ènìyàn.
L’insensé ne sera plus appelé noble, et on ne dira plus du fourbe qu’il est magnanime.
6 Nítorí òmùgọ̀ sọ̀rọ̀ òmùgọ̀, ọkàn rẹ̀ kún fún ìwà ibi: òun hùwà àìwà-bí-Ọlọ́run ó sì ń tan àṣìṣe tí ó kan Olúwa kalẹ̀; ẹni ebi ń pa ló fi sílẹ̀ lófo àti fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ ni ó mú omi kúrò.
Car l’insensé parle follement, et son cœur s’adonne à l’iniquité, pour faire des choses impies, et proférer des paroles fausses contre Yahweh, pour laisser avide l’âme de celui qui a faim, et ôter le breuvage à celui qui a soif.
7 Ibi ni gbogbo ọgbọ́n àwọn ìkà ènìyàn jẹ́, ó ń gba èrò búburú láti fi ọ̀rọ̀ èké pa tálákà run, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀bẹ̀ aláìní sì tọ̀nà.
Les armes du fourbe sont déloyales; il ourdit des intrigues, pour perdre les humbles par des mensonges, et le pauvre alors même qu’il parle justice.
8 Ṣùgbọ́n ọlọ́lá ènìyàn a máa pète ohun ńlá àti nípa èrò rere ni yóò dúró.
Mais le noble a de nobles desseins, et il se lèvera pour de nobles actions.
9 Ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ti gba ìtẹ́lọ́rùn gidi ẹ dìde kí ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ọkàn yín ti balẹ̀, ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ!
Femmes nonchalantes, levez-vous, écoutez ma voix! Filles sans souci, prêtez l’oreille à ma parole!
10 Ní ó lé díẹ̀ ní ọdún kan ẹ̀yin tí ọkàn an yín balẹ̀ yóò wárìrì; ìkórè àjàrà kò ní múnádóko, bẹ́ẹ̀ ni ìkórè èso kò ní sí.
Dans un an et quelques jours vous tremblerez, insouciantes, car il n’y aura pas de vendange; la récolte des fruits ne se fera pas.
11 Wárìrì, ẹ̀yin obìnrin onítẹ̀lọ́rùn; bẹ̀rù, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọbìnrin tí ẹ rò pé ọkàn yín balẹ̀! Ẹ bọ́ aṣọ yín kúrò, ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ yín.
Soyez dans l’effroi, nonchalantes! Tremblez, insouciantes! Otez vos riches vêtements, dépouillez-vous, ceignez vos reins de sacs.
12 Ẹ lu ọmú yín fún pápá ìgbádùn náà, fún àwọn àjàrà eléso
On se lamente, en se frappant le sein, sur les belles campagnes, sur les vignes fécondes.
13 àti fún ilẹ̀ àwọn ènìyàn mi, ilẹ̀ tí ó ti kún fún ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, bẹ́ẹ̀ ni, kẹ́dùn fún gbogbo ilé ìtura àti fún ìlú àríyá yìí.
Sur la terre de mon peuple croissent les épines et les ronces, même sur toutes les maisons de plaisir de la cité joyeuse.
14 Ilé olódi ni a ó kọ̀sílẹ̀, ìlù aláriwo ni a ó kọ̀ tì; ilé olódi àti ilé ìṣọ́ ni yóò di ihò títí láéláé, ìdùnnú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti pápá oko fún àwọn ẹran ọ̀sìn,
Car le palais est abandonné, la ville bruyante est devenue une solitude; Ophel et la Tour de garde servent à jamais de repaires, de lieux d’ébats aux ânes sauvages, et de pâturage aux troupeaux.
15 títí a ó fi tú Ẹ̀mí sí wa lórí láti òkè wá, àti ti aṣálẹ̀ tí yóò dí pápá oko ọlọ́ràá àti tí pápá ọlọ́ràá yóò dàbí ẹgàn.
Jusqu’à ce que soit répandu sur nous un esprit d’en haut, et que le désert devienne un verger, et que le verger soit réputé une forêt.
16 Ẹ̀tọ́ yóò máa gbé ní inú aṣálẹ̀ àti òdodo yóò sì máa gbé ní pápá oko ọlọ́ràá.
Alors la droiture habitera dans le désert, et la justice s’établira dans le verger,
17 Èso òdodo náà yóò sì jẹ́ àlàáfíà; àbájáde òdodo yóò sì jẹ́ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé títí láé.
Et le produit de la justice sera la paix, et le fruit de la justice le repos et la sécurité pour jamais.
18 Àwọn ènìyàn mi yóò máa gbé ní ibùgbé àlàáfíà, ní ibùgbé ìdánilójú, ní àwọn ibi ìsinmi tí ó parọ́rọ́.
Mon peuple habitera dans un séjour de paix, dans des habitations sûres, dans des demeures tranquilles.
19 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé yìnyín ti tẹ́jú igbó pẹrẹsẹ àti tí ojú ìlú ti tẹ́ pẹrẹsẹ pátápátá,
Mais la forêt sera tombée sous la grêle, et la ville profondément abaissée.
20 báwo ni ẹ ó ti jẹ́ alábùkún tó, nípa gbígbin irúgbìn sí ipa odò gbogbo, àti nípa jíjẹ́ kí àwọn màlúù yín àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ jẹ láìsí ìdíwọ́.
Heureux, vous qui semez partout près des eaux et qui laissez en liberté le pied du bœuf et de l’âne!