< Isaiah 31 >
1 Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́, tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn, ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì, tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.
Wonnue, wɔn a wɔkɔ Misraim kɔhwehwɛ mmoa, wɔn a wɔde wɔn ho to apɔnkɔ so, wɔn a wogye wɔn nteaseɛnam dodow ne wɔn apɔnkɔsotefo ahoɔden mmoroso no di, na wɔnhwɛ Israel Kronkronni no, anaasɛ wɔmpɛ mmoa mfi Awurade hɔ.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá; òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ. Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà, àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.
Nanso Awurade yɛ onyansafo a obetumi de ɔhaw aba; ɔnsesa nʼano. Ɔbɛsɔre atia amumɔyɛfo fi, ne wɔn a wɔboa nnebɔneyɛfo.
3 Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti wọn kì í ṣe Ọlọ́run; ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí. Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde, ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀, ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú; àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.
Na Misraimfo yi yɛ nnipa kɛkɛ, wɔnyɛ Onyankopɔn. Wɔn apɔnkɔ yɛ ɔhonam na wɔnyɛ honhom. Sɛ Awurade teɛ ne nsa a, ɔboafo bɛwatiri na nea wɔboa no no bɛhwe ase; wɔn baanu bɛbɔ mu asɛe.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀ bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀, ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.
Sɛɛ na Awurade ka kyerɛ me: “Sɛnea gyata woro so, sɛnea gyata kokroo woro so gu ne hanam so no a mpo sɛ wɔfrɛ nguanhwɛfo dɔm kɔ no so a, wɔn nteɛteɛmu mmɔ no hu na wɔn huuyɛ nso nhaw no no, saa ara na Asafo Awurade besian abɛko wɔ Sion Bepɔw ne ne sorɔnsorɔmmea so.
5 Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu, Òun yóò dáàbò bò ó, yóò sì tú u sílẹ̀ Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀.”
Sɛnea nnomaa tu gyina faako wɔ wim no saa ara na Asafo Awurade bɛbɔ Yerusalem ho ban; ɔbɛbɔ ne ho ban na wagye no, obegyaa no na wagye no asi hɔ.”
6 Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.
Monsan nkɔ nea moayɛ dɔm atia no no nkyɛn, Israelfo.
7 Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.
Da no mo mu biara bɛpo dwetɛ ne sikakɔkɔɔ ahoni a mode mo nsa a ɛho agu fi ayɛ no.
8 “Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá; idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n. Wọn yóò sì sá níwájú idà náà àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.
“Asiria bɛhwe ase wɔ afoa a ɛnyɛ onipa de ano; afoa a ɛnyɛ onipa de bɛsɛe wɔn. Wobeguan afi afoa no ano na wɔbɛma wɔn mmerante ayɛ ɔhyɛ adwuma.
9 Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù; àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,” ni Olúwa wí, ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni, ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.
Wɔn abandennen bebubu, ehu nti; wohu akofo frankaa a, wɔn asraafo mpanyimfo bɛbɔ huboa,” sɛɛ na Awurade se, nea ne gya wɔ Sion, na ne fononoo si Yerusalem no.