< Isaiah 31 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́, tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn, ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì, tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.
Вай де чей че се кобоарэ ын Еӂипт дупэ ажутор, се бизуе пе кай ши се ынкред ын мулцимя карелор ши ын путеря кэлэрецилор, дар ну привеск спре Сфынтул луй Исраел ши ну каутэ пе Домнул!
2 Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá; òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ. Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà, àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.
Дар ши Ел есте ынцелепт ши адуче ненорочиря ши ну Ышь я ворбеле ынапой, чи Се ридикэ ымпотрива касей челор рэй ши ымпотрива ажуторулуй челор че сэвыршеск нелеӂюиря.
3 Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti wọn kì í ṣe Ọlọ́run; ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí. Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde, ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀, ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú; àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.
Кэч еӂиптянул есте ом, ну Думнезеу, ши каий луй сунт карне, ну дух. Доар мына сэ-Шь ынтиндэ Домнул, ши окротиторул се ва клэтина, яр чел окротит ва кэдя ши вор пери ку тоций.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀ bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀, ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.
Кэч аша мь-а ворбит Домнул: „Кум муӂеск леул ши пуюл де леу асупра прэзий, ын чуда тутурор пэсторилор стрыншь ымпотрива лор, ши ну се ынспэймынтэ де гласул лор, нич ну се сперие де нумэрул лор, аша Се ва коборы ши Домнул оштирилор сэ лупте пе мунтеле Сионулуй ши пе дялул луй.
5 Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu, Òun yóò dáàbò bò ó, yóò sì tú u sílẹ̀ Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀.”
Кум ышь ынтинд пэсэриле арипиле песте пуий лор, аша ва окроти Домнул оштирилор Иерусалимул, ыл ва окроти ши-л ва избэви, ыл ва круца ши-л ва мынтуи.”
6 Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.
Ынтоарчеци-вэ ла Ачела де ла каре в-аць абэтут мулт, копий ай луй Исраел!
7 Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.
Кэч, ын зиуа ачея, фиекаре ышь ва лепэда идолий де арӂинт ши де аур пе каре ви й-аць фэкут ку мыниле воастре нелеӂюите.
8 “Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá; idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n. Wọn yóò sì sá níwájú idà náà àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.
„Ши асириянул ва кэдя учис де о сабие, дар ну а унуй ом: ыл ва нимичи о сабие, дар ну есте а унуй ом; ва фуӂи де сабие ши тинерий луй рэзбойничь вор фи робиць.
9 Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù; àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,” ni Olúwa wí, ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni, ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.
Стынка луй се ва топи де гроазэ, ши кэпетенииле луй вор тремура ынаинтя стягулуй”, зиче Домнул, каре Ышь аре фокул ын Сион ши купторул ын Иерусалим.

< Isaiah 31 >