< Isaiah 31 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́, tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn, ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì, tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.
Ak vai, tiem, kas uz Ēģipti iet pēc palīdzības un paļaujas uz zirgiem un cerē uz ratiem, tāpēc ka to ir daudz, un uz jātniekiem, tāpēc ka to ir liels pulks, bet uz to Svēto iekš Israēla nerauga un To Kungu nemeklē.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá; òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ. Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà, àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.
Bet arī Viņš ir gudrs un liek ļaunumam nākt un neņem atpakaļ Savus vārdus, bet ceļas pret bezdievīgo namu un pret ļauna darītāju palīgu.
3 Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti wọn kì í ṣe Ọlọ́run; ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí. Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde, ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀, ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú; àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.
Jo ēģiptieši ir cilvēki un ne Dievs, un viņu zirgi ir miesa un ne gars. Un Tas Kungs izstieps Savu roku, un tas palīgs klūp un, kam top līdzēts, tas krīt, un tie visi kopā iet bojā.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀ bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀, ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.
Jo tā Tas Kungs uz mani sacījis: tā kā lauva un kā jauns lauva rūc par savu laupījumu, un, jebšu pret viņu liels ganu pulks top sasaukts, tomēr viņš neizbīstas priekš viņu balss un nebaidās no viņa lielā pulka, tāpat Tas Kungs Cebaot nolaidīsies, karot uz Ciānas kalna un uz viņas augstuma.
5 Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu, Òun yóò dáàbò bò ó, yóò sì tú u sílẹ̀ Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀.”
Tā kā putni lidinājās, tāpat Tas Kungs Cebaot apklās Jeruzālemi, un apklādams izpestīs un žēlodams izglābs.
6 Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.
Atgriežaties, Israēla bērni, pie Tā, no kā tik tālu esat atkāpušies.
7 Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.
Jo tai dienā tie atmetīs ikkatrs savus sudraba elkus un savus zelta elkus, ko jūsu rokas ir taisījušas sev par grēku.
8 “Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá; idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n. Wọn yóò sì sá níwájú idà náà àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.
Un Asurs kritīs caur zobenu, bet ne caur vīra zobenu, un to norīs, bet ne cilvēka zobens, un tas bēgs no zobena un viņa jaunekļi paliks par vergiem.
9 Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù; àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,” ni Olúwa wí, ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni, ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.
Un viņa kalns trīcēs no bailēm, un viņa lielkungi iztrūcināti bēgs no karoga; to saka Tas Kungs, kam Ciānā uguns un Jeruzālemē ugunskurs.

< Isaiah 31 >