< Isaiah 31 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́, tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn, ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì, tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.
Anunae bomnah dang ham Egypt aka suntlak thil rhoek aih, marhang dongah hangdang uh tih leng dongah pangtung uh. Ping uh tih marhang caem neh tahoeng uh aih. Te dongah Israel kah a cim taengla mang uh pawt tih Yahovah te dawtlet uh pawh.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá; òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ. Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà, àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.
Tedae BOEIPAamah khaw a cueih dongah yoethae a thoeng sak thai. A ol khaw a yueh voel pawt dongah thaehuet imkhui neh boethae aka saii kah bomkung te a tlai thil ni.
3 Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti wọn kì í ṣe Ọlọ́run; ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí. Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde, ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀, ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú; àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.
Egypt te hlang ni, Pathen moenih. Amih kah marhang te pumsa ni mueihla moenih. BOEIPA loh a kut a thueng atah aka bom kung te paloe vetih a bom hlang te khaw cungku ni. Te vaengah amih te a rhenten la boeih hmata uh ni.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀ bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀, ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.
Te dongah sathueng neh cathueng ca loh a maeh a nguel thil bangla BOEIPA loh kai taengah a thui. Boiva aka dawn te rhoihui la a khue thil dae amih ol ah rhihyawp pawt tih amih hlangping long khaw a paa sak moenih. Te dongah caempuei BOEIPA tah Zion tlang neh som te muk hamla ha suntla ni.
5 Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu, Òun yóò dáàbò bò ó, yóò sì tú u sílẹ̀ Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀.”
Vaa bangla lam tangloeng tih caempuei BOEIPA loh Jerusalem a tungaep ni. A tungaep vetih a huul ni. A kan vetih a loeih sak ni.
6 Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.
Koeknah dongah aka muelh Israel ca rhoek aw, amah taengla mael uh laeh.
7 Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.
Tekah khohnin ah tah hlang boeih loh amah cakhli mueirhol, namamih kah tholhnah ham na kut loh a saii uh a sui mueirhol te a hnawt uh ni.
8 “Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá; idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n. Wọn yóò sì sá níwájú idà náà àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.
Assyria te hlang pawt kah cunghang dongah cungku vetih tongpa pawt kah cunghang loh anih te a hlap ni. cunghang taeng lamloh a rhaelrham vaengah a tongpang rhoek te saldong la om uh ni.
9 Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù; àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,” ni Olúwa wí, ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni, ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.
A thaelpang khaw rhihnah loh a poe vetih a mangpa rhoek te rholik kongah rhihyawp uh ni. BOEIPA kah olphong tah Zion ah amah kah hmaipuei la, Jerusalem ah amah kah hmaipom la a pak ni.

< Isaiah 31 >