< Isaiah 30 >

1 “Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
RAB, “Vay haline bu dikbaşlı soyun!” diyor, “Benim değil, kendi tasarılarını yerine getirip Ruhuma aykırı anlaşmalar yaparak Günah üstüne günah işliyorlar.
2 tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
Bana danışmadan firavunun koruması altına girmek, Mısır'ın gölgesine sığınmak için oraya gidiyorlar.
3 Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
Ne var ki, firavunun koruması onlar için utanç, Mısır'ın gölgesine sığınmaları onlar için rezillik olacak.
4 Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
Önderleri Soan'da olduğu, Elçileri Hanes'e ulaştığı halde,
5 gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
Kendilerine yararı olmayan bir halk yüzünden hepsi utanacak. O halkın onlara ne yardımı ne de yararı olacak, Ancak onları utandırıp rezil edecek.”
6 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
Negev'deki hayvanlara ilişkin bildiri: “Elçiler erkek ve dişi aslanların, Engereklerin, uçan yılanların yaşadığı Çetin ve sıkıntılı bir bölgeden geçerler. Servetlerini eşeklerin sırtına, Hazinelerini develerin hörgücüne yükleyip Kendilerine hiç yararı olmayan halka taşırlar.
7 sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
Mısır'ın yardımı boş ve yararsızdır, Bu yüzden Mısır'a ‘Haylaz Rahav’ adını verdim.
8 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
“Şimdi git, söylediğimi onların önünde Bir levhaya yazıp kitaba geçir ki, Gelecekte kalıcı bir tanık olsun.
9 Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
Çünkü o asi bir halk, yalancı bir soy, RAB'bin yasasını duymak istemeyen bir soydur.
10 Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
Bilicilere, ‘Artık görüm görmeyin’, Görenlere, ‘Bizim için doğru şeyler görmeyin, Bize güzel şeyler söyleyin, asılsız şeyler açıklayın’ diyorlar,
11 Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
‘Yoldan çekilin, yolu açın, Bizi İsrail'in Kutsalı'yla yüzleştirmekten vazgeçin.’”
12 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
Bu nedenle İsrail'in Kutsalı diyor ki, “Madem bu bildiriyi reddettiniz, Baskıya ve hileye güvenip dayandınız;
13 ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
Bu suçunuz yüksek bir surda Sırt veren çatlağa benziyor. Böyle bir sur birdenbire yıkılıverir.
14 Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
O, toprak çömlek gibi parçalanacak. Parçalanması öyle şiddetli olacak ki, Ocaktan ateş almaya ya da sarnıçtan su çıkarmaya Yetecek büyüklükte bir parça kalmayacak.”
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
Egemen RAB, İsrail'in Kutsalı şöyle diyor: “Bana dönün, huzur bulun, kurtulursunuz. Kaygılanmayın, bana güvenin, güçlü olursunuz. Ama bunu yapmak istemiyorsunuz.
16 Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
‘Hayır, atlara binip kaçarız’ diyorsunuz, Bu yüzden kaçmak zorunda kalacaksınız. ‘Hızlı atlara bineriz’ diyorsunuz, Bu yüzden sizi kovalayanlar da hızlı olacak.
17 Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
Bir kişinin tehdidiyle bin kişi kaçacak, Beş kişinin tehdidiyle hepiniz kaçacaksınız; Dağ başında bir gönder, Tepede bir sancak gibi kalana dek kaçacaksınız.
18 Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
“Yine de RAB size lütfetmeyi özlemle bekliyor, Size merhamet göstermek için harekete geçiyor. Çünkü RAB adil Tanrı'dır. Ne mutlu O'nu özlemle bekleyenlere!”
19 Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
“Ey Yeruşalim'de oturan Siyon halkı, Artık ağlamayacaksın! Feryat ettiğinde Rab sana nasıl da lütfedecek! Feryadını duyar duymaz seni yanıtlayacak.
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
Rab ekmeği sıkıntıyla, Suyu cefayla verse de, Öğretmeniniz artık gizlenmeyecek, Gözünüzle göreceksiniz onu.
21 Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
Sağa ya da sola sapacağınız zaman, Arkanızdan, ‘Yol budur, bu yoldan gidin’ Diyen sesini duyacaksınız.
22 Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
Gümüş kaplı oyma putlarınızı, Altın kaplama dökme putlarınızı ‘Kirli’ ilan edecek, Kirli bir âdet bezi gibi atıp ‘Defol’ diyeceksiniz.
23 Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
Rab toprağa ektiğiniz tohum için yağmur verecek, Toprağın ürünü olan yiyecek bol ve zengin olacak. O gün sığırlarınız geniş otlaklarda otlanacak.
24 Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
Toprağı işleyen öküzlerle eşekler Kürekle, yabayla savrulmuş, Tuzlanmış yem yiyecekler.
25 Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
Kulelerin yıkıldığı o büyük kıyım günü Her yüksek dağda, her yüce tepede Akarsular olacak.
26 Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
RAB halkının kırıklarını sardığı, Vuruşuyla açtığı yaraları iyileştirdiği gün, Ay güneş gibi parlayacak, Güneş yedi kat, yedi günün toplam parlaklığı kadar parlak olacak.”
27 Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
Bakın, RAB'bin kendisi uzaktan geliyor, Kızgın öfkeyle kara bulut içinde. Dudakları gazap dolu, Dili her şeyi yiyip bitiren ateş sanki.
28 Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
Soluğu adam boynuna dek yükselmiş taşkın ırmak gibi. Ulusları elekten geçirecek, değersizleri ayıracak, Halkların ağzına yoldan saptıran bir gem takacak.
29 Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
Ama sizler bayram gecesini kutlar gibi Ezgiler söyleyeceksiniz. RAB'bin dağına, İsrail'in Kayası'na Kaval eşliğinde çıktığınız gibi İçten sevineceksiniz.
30 Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
RAB heybetli sesini işittirecek; Kızgın öfkeyle, her şeyi yiyip bitiren ateş aleviyle, Sağanak yağmurla, fırtına ve doluyla Bileğinin gücünü gösterecek.
31 Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
Asur RAB'bin sesiyle dehşete düşecek, O'nun değneğiyle vurulacak.
32 Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
RAB'bin terbiye değneğiyle onlara indirdiği her darbeye Tef ve lir eşlik edecek. RAB silahlarını savura savura onlarla savaşacak.
33 A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.
Tofet çoktan hazırlandı, Evet, kral için hazırlandı. Geniş ve yüksektir odun yığını, Ateşi, odunu boldur. RAB kızgın kükürt selini andıran Soluğuyla tutuşturacak onu.

< Isaiah 30 >