< Isaiah 30 >

1 “Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
Malheur à vous, enfants rebelles! dit le Seigneur; vous avez tenu conseil, et ce n'est pas avec moi; vous avez pris des résolutions, et ce n'est pas avec mon Esprit; vous entassez péchés sur péchés,
2 tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
O vous qui êtes partis pour descendre en Égypte, sans me consulter, pour demander du secours au Pharaon, et trouver un abri chez les Égyptiens.
3 Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
Car l'appui du Pharaon sera pour vous une honte; et l'opprobre attend ceux qui se reposent sur l'Égypte.
4 Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
Car vos princes sont allés à Tanis, messagers de malheur.
5 gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
Ils ont pris une peine inutile auprès d'un peuple qui ne les aidera point pour le secours, mais pour la confusion et l'opprobre.
6 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
Ils vont dans l'affliction et la détresse, là où il y a un lion et un lionceau, et d'où viennent aussi des aspics et des petits d'aspics volants; ils ont transporté sur des ânes et des chamelles leurs richesses près d'une nation qui ne les aidera point.
7 sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
Les Égyptiens vous donneront un secours vain et inutile; dis-leur: Cette consolation pour vous est vaine.
8 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
Maintenant donc, assieds-toi; écris ces choses sur le buis et dans un livre; car ce sera pour les jours de l'avenir et même pour tous les siècles.
9 Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
Parce que ce peuple est indocile; fils menteurs, qui ne veulent point écouter la loi de Dieu,
10 Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
Ils disent aux prophètes: Ne nous annoncez rien; ils disent à ceux qui ont des visions: Ne nous parlez pas; mais annoncez-nous quelque autre erreur.
11 Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
Détournez-nous de cette voie; ôtez-nous le sentier, ôtez-nous l'oracle d'Israël.
12 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
A cause de cela, voici ce que dit le Saint d'Israël: Parce que vous n'avez point obéi à ces paroles, parce que vous avez espéré dans le mensonge, parce que vous avez murmuré et que vous avez mis votre confiance en vos murmures;
13 ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
A cause de cela, ce péché sera pour vous comme un mur qui s'écroule soudain, lorsque est prise une ville dont la chute est inopinée.
14 Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
Et sa chute sera comme quand on brise un vase de poterie; les fragments en sont tels qu'on n'y peut trouver un tesson à transporter du feu, ou à puiser un peu d'eau.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
Voici ce que dit le Seigneur, le Seigneur saint d'Israël: Lorsque après t'être perverti tu te lamenteras, tu seras sauvé, et tu sauras où tu étais; car tu croyais en des vanités, des vanités étaient ta force, et tu n'as pas voulu m'entendre.
16 Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
Mais vous avez dit: nous fuirons à cheval; à cause de cela, vous fuirez. Vous avez dit: Nous serons sur des chevaux agiles; à cause de cela, ils seront agiles aussi les chevaux qui vous poursuivront.
17 Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
Mille des vôtres fuiront à la voix d'un seul ennemi; une multitude fuira à la voix de cinq hommes, jusqu'à ce que vous restiez comme un mât sur une montagne, ou comme la hampe qui porte un étendard sur une colline.
18 Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
Et Dieu vous attendra encore pour vous prendre en compassion; et en cela il signalera sa gloire en vous faisant miséricorde; car le Seigneur votre Dieu est le juge. Heureux ceux qui l'attendent!
19 Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
Car le peuple saint demeurera en Sion, et Jérusalem pleurera à chaudes larmes, disant: Ayez pitié de moi! Et le Seigneur aura pitié de toi, quand il t'aura vue crier et qu'il t'aura entendue.
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
Et le Seigneur vous donnera le pain de l'affliction et l'eau de la détresse; et ceux qui t'égarent n'approcheront plus de toi; car tes yeux verront ceux qui t'égarent.
21 Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
Et tes oreilles entendront les discours de ceux qui, derrière toi, t'auront égarée, disant: Voici la voie, suivons-la, soit à droite, soit à gauche.
22 Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
Alors tu souilleras les idoles argentées, et tu réduiras en poudre les idoles d'or, et tu les jetteras au loin comme l'eau des menstrues, et tu les repousseras comme la fange.
23 Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
Alors il tombera de la pluie sur les grains que tu auras semés; alors le pain des fruits de la terre sera plantureux et succulent. Et en ce jour tout bétail broutera dans des pâturages spacieux et fertiles.
24 Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
Et vos taureaux et vos bœufs de labour mangeront de la paille assaisonnée d'orge vannée.
25 Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
Et en ce jour l'eau coulera sur toute haute montagne, sur toute colline élevée, longue beaucoup d'hommes auront péri et que leurs tours seront tombées.
26 Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
Et la lumière de la lune sera comme la lumière du soleil; et la lumière du soleil sera septuple durant le jour, lorsque le Seigneur aura pansé les meurtrissures de son peuple, et guéri les douleurs de ses plaies.
27 Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
Voici que le nom du Seigneur arrive après un long temps; sa fureur est ardente; la parole de ses lèvres est pleine de gloire; sa parole est pleine de colère, et les transports de sa fureur dévorent comme le feu.
28 Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
Et son souffle, comme l'eau qui se précipite dans un vallon, montera jusqu'au cou; et il se divisera pour troubler les nations au sujet de leurs vaines erreurs; et l'erreur aussi les poursuivra, et les prendra en face.
29 Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
Ne devrez-vous pas alors être toujours en joie, et toujours entrer dans mes lieux saints, comme aux jours de fête? Ne devrez-vous pas, comme ceux qui se réjouissent, venir au son des flûtes sur la montagne du Seigneur, devant le Dieu d'Israël?
30 Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
Et le Seigneur fera entendre sa voix glorieuse, et la fureur de son bras, qui se manifestera par des transports de colère et une flamme dévorante; sa foudre éditera violemment comme de l'eau et de la grêle qui tombe avec impétuosité.
31 Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
Car les Assyriens seront vaincus à la voix du Seigneur, par la plaie dont il les frappera.
32 Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
Et c'est là ce qui lui arrivera de tous les alentours, de toute contrée d'où il espérait du secours, et en qui il se confiait; les peuples, au contraire, viendront le combattre au son des tambours et des cithares.
33 A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.
Car vous serez requis avant le temps, Seigneur; tout n'est-il pas préparé pour votre règne, un ravin profond, des arbres abattus, le feu et un vaste bûcher? La colère du Seigneur est comme une vallée embrasée par le soufre.

< Isaiah 30 >