< Isaiah 30 >

1 “Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
Anunae a cilsuep te saii hamla BOEIPA kah olphong soah thinthah camoe rhoek aih. Tedae kai lamkah neh mueirhoi a hloe moenih. Ka mueihla kah bal moenih. Te dongah tholh te tholh neh a khoengvoep.
2 tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
Pharaoh kah lunghim khuiah bakuep ham neh Egypt kah hlipkhup ah ying hamla Egypt aka suntlak thil tih aka cet rhoek loh kai kah olka he a dawt uh moenih.
3 Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
Tedae Pharaoh kah lunghim te nangmih ham yahpohnah la, Egypt hlipkhup ah yingnah te khaw mingthae la poeh ni.
4 Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
A mangpa rhoek loh Zoan ah om uh tih a puencawn rhoek loh Hanes ham ben uh cakhaw,
5 gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
pilnam te a hoeikhang pah voel pawt tih bomkung la a om pawt neh a hoeikhang pawt dongah boeih a borhim vetih yah a bai ni. Te dongah yahpohnah neh kokhahnah la om bal ni.
6 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
Citcai khohmuen kah tuithim rhamsa ham olrhuh, sathuengnu a la neh sathueng lamkah, rhulthae neh minyuk aka ding kongah khobing coeng. A khuehtawn te laak kah a nam ah, a thakvoh te kalauk phuu dongah aka phuei rhoek he pilnam ham a hoeikhang moenih.
7 sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
Egypt long khaw a honghi neh a poeyoek lam ni a bom. Te dongah amih te, “Hoeng hoep Rahab,” la ka khue coeng.
8 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
Paan laeh, amih ham te cabael dongah daek lamtah, a cabu dongah tarhit pah laeh. Te daengah ni hmailong khohnin ham khaw, kumhal duela a om yoeyah eh.
9 Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
Laithae koca rhoek kah a ca rhoek, boekoek pilnam aih he, BOEIPA kah olkhueng tah hnatun ham huem uh pawh.
10 Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
Khohmu taengah, “Na hmuh pawt nim?” Tonghma rhoek taengah khaw kaimih ham oldueng na hmuh pawt nim?, phoknah na hmuh uh akhaw kaimih ham a hnal la thui uh.
11 Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
Longpuei lamloh nong uh, caehlong lamloh khoe uh. Israel kah a Cim te mamih mikhmuh lamloh kangkuen saeh,” a ti uh.
12 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
Te dongah Israel kah a cim loh, “Hekah olka he na sit uh. Hnaemtaeknah dongah na pangtung uh tih khohmang neh a soah na pangnal uh.
13 ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
Te dongah nangmih taengah tathaesainah he khaw vongtung dongah a puut loh a yam tih a cungku bangla ha om ni. Aka pomdoep uh khaw a pocinah lam ni buengrhuet a om pahoi mai.
14 Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
Amsai loh tuitang kaek a dae banghui la rhek vetih lungma ti mahpawh. Hmai rhong dongkah hmai soh ham neh kangueng lamkah tui bak nah ham kangna khaw paikaek kah a kaek te hmu mahpawh.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
Te dongah ni Israel kah a cim ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Maelnah neh mongnah dongah a mong la n'khang coeng tih ueppangnah dongah na thayung thamal khaw om dae ta na ngaih uh pawh.
16 Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
Te phoeiah, “Moenih, te ham te marhang dongah ka rhaelrham uh bitni,” na ti uh. Na rhaelrham uh vaengah, “Yanghoep la n'ngol uh,” na ti uh dongah nangmih aka hloem rhoek khaw yanghoep uh van ni.
17 Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
Tlang lu kah cungkui bangla, som sokah rholik bangla na cul uh hil pakhat kah tluungnah dongah, panga kah tluungnah dongah khaw thawng khat la na rhaelrham uh ni.
18 Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
Tedae BOEIPA loh nangmih rhen ham n'rhingda tangloeng tih nangmih aka haidam la pomsang uh tangkhuet. Tiktamnah Pathen Yahovah amah te aka rhingda boeih tah a yoethen.
19 Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
Jerusalem kah khosa Zion pilnam aw na rhap rhoe na rhap voel mahpawh. Na pang ol te a yaak vaengah n'rhen rhoe, n'rhen vetih nang te n'doo ni.
20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
Boeipa loh nang te rhal kah buh neh hnaemtaeknah tui m'pae cakhaw na saya rhoek te khaw khoe mahpawh. Tedae na saya aka hmu rhoek te na mik ah om bitni.
21 Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
Na hnuk lamkah ol loh, “Longpuei he bantang ah khaw, banvoei ah khaw cet mailai,” a ti te na hna loh a yaak bitni.
22 Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
Na cak ben mueidaep neh, na sui mueihloe pholip khaw na poeih ni. Te rhoek te na pumthim hainak bangla thaek uh vetih, “Acih hoeih,” na ti ni.
23 Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
Te vaengah khohmuen kah na tuh na cangti te khotlan loh a suep ni. Khohmuen kah cangpai buh neh kuirhang la na om ni. Tekah khohnin ah tah rhamtlim dangka ah na boiva loh pulpulh luem ni.
24 Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
Diklai kah aka tho aka tat saelhung neh laak pataeng cangcopcung neh, rha neh a hlaih canghlaih, kamvuelh ni a caak eh.
25 Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
Tlang sang tom ah khaw, som tom ah khaw ana om saeh. Rhaltoengim a cungku ham vaengkah ngawnnah a len khohnin ah sokca rhahlawn tui loh phul coeng.
26 Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
Hla kah a vang te khomik kah a vang bangla om ni. Khomik kah a vang khaw khohnin hnin rhih kah a vang bangla a pueh parhih la om ni. BOEIPA long tah a pilnam kah a tlawt te a poi pah tih a hmapuei hmasoe khaw a hoeih sak.
27 Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
BOEIPA kah a ming tah khohla bangsang lamkah a thintoek aka ung khui lamkah ha thoeng coeng ke. A hmuilai kah kosi hmaihu te a thah la baetawt tih a ol khaw hmai bangla tak.
28 Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
A hil khaw rhawn duela a muelh tih aka yo soklong la, namtom te poeyoek khamyai ah vairhuek la, pilnam kam dongkah a hmaang kamrhui la.
29 Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
Laa khaw nangmih taengah tah khotue a ciim hlaem kah bangla om vetih, BOEIPA tlang kah Israel lungpang paan hamla phitphoet neh aka thoeih bangla thinko kah kohoenah khaw om ni.
30 Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
A ol mueithennah te BOEIPA loh n'yaak sak vetih, hmaihluei aka hlawp rhonam, hlipuei neh rhaelnu lungto, thintoek thinkoeh dongah a ban loh a mong la m'hmuh sak ni.
31 Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
BOEIPA ol loh Assyria te a rhihyawp sak vetih, mancai neh a ngawn ni.
32 Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
BOEIPA loh a ning a hol pah vaengah a pum dongkah kamrhing te khaw, rhotoeng khaw caitueng kah lamkai la boeih a poeh pah. Te vaengah caemtloek kah thueng hmueih loh amih te a vathoh thil ni.
33 A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.
Tophet khaw hlaemvai lamkah ni rhong a pai thil coeng. Te khaw manghai ham a soepsoei pah rhoe. A hlanhmai te a dung a ka sak tih hmai te khaw thing muep a hueng thil. BOEIPA kah a hiil loh kat hmai soklong bangla te te a dom.

< Isaiah 30 >