< Isaiah 3 >

1 Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
Ty se, Herren, HERREN Sebaot skall taga bort ifrån Jerusalem och Juda allt slags stöd och uppehälle -- all mat till uppehälle och all dryck till uppehälle --
2 Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
hjältar och krigsmän, domare och profeter, spåmän och äldste,
3 balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
underhövitsmän och högtuppsatta män, rådsherrar och slöjdkunnigt folk och män som äro förfarna i besvärjelsekonst.
4 “Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
Och jag skall giva dem ynglingar till furstar, och barnsligt självsvåld skall få råda över dem.
5 Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
Av folket skall den ene förtrycka den andre, var och en sin nästa; den unge skall sätta sig upp mot den gamle, den ringe mot den högt ansedde.
6 Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
När då så sker, att någon fattar tag i en annan i hans faders hus och säger: "Du äger en mantel, du skall bliva vår styresman; tag du hand om detta vacklande rike" --
7 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
då skall denne svara och säga: "Jag kan icke skaffa bot; i mitt hus finnes varken bröd eller mantel. Mig skolen I icke sätta till styresman över folket."
8 Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
Ty Jerusalem vacklar, och Juda faller, då de nu med sitt tal och sina gärningar stå emot HERREN och äro gensträviga mot hans härlighets blickar.
9 Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
Deras uppsyn vittnar emot dem; och likasom Sodoms folk bedriva de sina synder uppenbart och dölja dem icke. Ve över deras själar, ty själva hava de berett sig olycka!
10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
Om den rättfärdige mån I tänka att det skall gå honom väl, ty sådana skola äta sina gärningars frukt.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
Men ve över den ogudaktige! Honom skall det gå illa, ty efter hans gärningar skall hans vedergällning bliva.
12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
Mitt folks behärskare är ett barn, och kvinnor råda över det. Mitt folk, dina ledare föra dig vilse och fördärva den väg, som du skulle gå.
13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
Men HERREN står redo att gå till rätta, han träder fram för att döma folken;
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
HERREN vill gå till doms med sitt folks äldste och med dess furstar. "I haven skövlat vingården; rov från de fattiga är i edra hus.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Huru kunnen I så krossa mitt folk och söndermala de fattiga?" Så säger Herren, HERREN Sebaot.
16 Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
Och HERREN säger: Eftersom Sions döttrar äro så högmodiga, och gå med rak hals och spela med ögonen, och gå där och trippa och pingla med sina fotringar,
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
därför skall Herren låta Sions döttrars hjässor bliva fulla av skorv, och HERREN skall blotta deras blygd.
18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
På den dagen skall Herren taga bort all deras ståt: fotringar, pannband och halsprydnader,
19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
örhängen, armband och slöjor,
20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
huvudprydnader, fotstegskedjor, gördlar, luktflaskor och amuletter,
21 òrùka ọwọ́ àti ti imú,
fingerringar och näsringar,
22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
högtidsdräkter, kåpor, mantlar och pungar,
23 dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
speglar, fina linneskjortor, huvudbindlar och flor.
24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
Och där skall vara stank i stället för vällukt, rep i stället för bälte, skalligt huvud i stället för krusat hår, hölje av säcktyg i stället för högtidsmantel, märken av brännjärn i stället för skönhet.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
Dina män skola falla för svärd och dina hjältar i krig:
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.
hennes portar skola klaga och sörja, och övergiven skall hon sitta på marken.

< Isaiah 3 >