< Isaiah 3 >
1 Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
Oto bowiem Pan, PAN zastępów, odbierze Jerozolimie i Judzie podporę i laskę, wszelką podporę w chlebie i wszelką podporę w wodzie.
2 Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
Mocarza i męża walecznego, sędziego i proroka, mędrca i starca;
3 balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
Dowódcę pięćdziesiątki i dostojnika, doradcę, wybitnego rzemieślnika i krasomówcę.
4 “Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
Książętami ustanowię chłopców, dzieci będą panować nad nimi.
5 Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
Ludzie będą gnębić jeden drugiego, każdy swego bliźniego. Dziecko powstanie przeciwko starcowi, a podły przeciwko dostojnikowi.
6 Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
Gdy człowiek uchwyci się swego brata z domu swego ojca i [powie]: Masz ubranie, bądź naszym wodzem, niech te ruiny będą pod twoją ręką;
7 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
Ten przysięgnie w tym dniu, mówiąc: Nie będę opatrywał [tych ran]; w moim domu bowiem nie ma chleba ani ubrania; nie czyńcie mnie wodzem ludu.
8 Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
Bo Jerozolima upada, a Juda się wali, gdyż ich język i czyny są przeciwko PANU, aby pobudzić do gniewu oczy jego majestatu.
9 Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
Wyraz ich twarzy świadczy przeciwko nim; jak Sodoma ogłaszają swój grzech, nie kryją [go]. Biada ich duszy! Gdyż sami na siebie sprowadzają zło.
10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
Powiedzcie sprawiedliwemu, że będzie mu dobrze, bo będzie spożywać owoc swoich rąk.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
Biada niegodziwemu! Będzie mu źle, odpłacą [mu] bowiem według [czynów] jego rąk.
12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
Ciemięzcami mego ludu są dzieci i kobiety nim rządzą. O ludu mój! Twoi wodzowie cię zwodzą i niszczą drogę twoich ścieżek.
13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
PAN powstał, aby się rozprawić, stoi, aby sądzić lud.
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
PAN stawi na sąd starszych swego ludu i ich książąt: Wy spustoszyliście [moją] winnicę, w waszych domach znajduje się łup ubogich.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Po co miażdżycie mój lud i uciskacie oblicza ubogich? – mówi Pan BÓG zastępów.
16 Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
PAN powiedział: Ponieważ wynoszą się córki Syjonu i chodzą z wyciągniętą szyją, uwodzą oczami, a chodząc, drepczą i pobrzękują swoimi nogami;
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
Dlatego Pan ogoli wierzch głowy córek Syjonu i PAN obnaży ich nagość.
18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
W tym dniu Pan odejmie ozdobne brzękadła [od ich stóp], ich czepce i księżyce;
19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
Łańcuszki, bransolety i welony;
20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
Czapeczki, ozdoby u nóg, opaski, naszyjniki i kolczyki;
21 òrùka ọwọ́ àti ti imú,
Pierścionki i wisiorki na czołach;
22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
Odświętne szaty, płaszcze, szale i torebki;
23 dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
Zwierciadełka, bisior, turbany i narzutki.
24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
I wtedy zamiast wonności będzie smród, zamiast pasa będzie rozdarcie, zamiast upiętych włosów będzie łysina, zamiast szerokiej szaty będzie przepasanie worem i zamiast piękna będzie oparzenie.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
Twoi mężczyźni polegną od miecza i twoi mocarze – na wojnie.
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.
Jej bramy zasmucą się i zapłaczą, a [ona], spustoszona, usiądzie na ziemi.