< Isaiah 3 >
1 Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
Albowiem oto panujący Pan zastępów odejmie od Jeruzalemu i od Judy łaskę, i podporę, wszelaką podporę chleba, i wszelaką podporę wody.
2 Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
Mocarza i męża walecznego, i sędziego, i proroka, i mędrca, i starca;
3 balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
Rotmistrza nad pięćdziesiąt, a męża poważnego, i radcę, i mądrego rzemieślnika, i krasomówcę.
4 “Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
I dam im dzieci za książęta; dzieci mówię panować będą nad nimi.
5 Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
I będzie uciskał między ludem jeden drugiego, i bliźni bliźniego swego: powstanie dziecię przeciwko starcowi, a podły przeciwko zacnemu.
6 Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
A gdy się uchwyci każdy brata swego z domu ojca swego, i rzecze: Masz odzienie, bądźże książęciem naszym, a upadek ten zatrzymaj ręką swą:
7 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
Tedy on przysięże dnia onego, mówiąc: Nie będę zawiązywał tych ran: albowiem w domu moim niemasz chleba, ani odzienia; nie stanowcież mię książęciem nad ludem.
8 Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
Bo Jeruzalem upada, a Juda się wali, dlatego, że język ich, i sprawy ich są przeciwko Panu, pobudzając do gniewu oczy majestatu jego.
9 Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
Postawa oblicza ich świadczy przeciwko nim; grzech swój, jako Sodomczycy, opowiadają, a nie tają go. Biada duszy ich! albowiem sami na się złe przywodzą.
10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
Powiedzcie sprawiedliwemu, że mu dobrze będzie; bo owocu uczynków swoich pożywać będzie.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
Ale biada niepobożnemu! źle mu będzie; albowiem odpłata rąk jego dana mu będzie.
12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
Książęta ludu mego są dziećmi, a niewiasty panują nad nimi. O ludu mój! ci, którzy cię wodzą, zwodzą cię, a drogę ścieżek twoich ukrywają.
13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
Powstał Pan, aby sądził, stoi, aby sądził lud.
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
Pan przyjdzie na sąd przeciwko starszym ludu swego, i przeciwko książętom ich, a rzecze: Wyście spustoszyli winnicę moję, zdzierstwo z ubogiego w domach waszych.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Przeczże trzecie lud mój, a oblicza ubogich bijecie? mówi Pan, Pan zastępów.
16 Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
I rzekł Pan: Iż się wynoszą córki Syońskie, a chodzą szyje wyciągnąwszy, i mrugając oczyma przechodzą się, a drobno postępując nogami swemi szelest czynią:
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
Przetoż obłysi Pan wierzch głowy córek Syońskich, a Pan sromotę ich obnaży.
18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
Dnia onego odejmie Pan ochędóstwo podwiązek, także czepce i zawieszenia,
19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
Piżmowe jabłka, i manele, i zatyczki,
20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
Bieretki, i zapony, i bindy, i przedniczki, i nausznice;
21 òrùka ọwọ́ àti ti imú,
Pierścionki, i naczelniki,
22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
Odmienne szaty, i płaszczyki, i podwiki, i wacki,
23 dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
Zwierciadła, i rantuszki, i tkanki, i letniki.
24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
I będzie miasto wonnych rzeczy smród, a miasto pasa rozpasanie, a miasto utrefionych włosów łysina, a miasto szerokiej szaty opasanie worem, a miasto piękności ogorzelina.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
Mężowie twoi od miecza upadną, a mocarze twoi w bitwie.
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.
I zasmucą się, a płakać będą bramy jego, a spustoszony na ziemi siedzieć będzie.