< Isaiah 3 >

1 Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
Car voici, le Seigneur, l'Eternel des armées, s'en va ôter de Jérusalem et de Juda le soutien et l'appui, tout soutien de pain, et tout soutien d'eau.
2 Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
L'homme fort, et l'homme de guerre, le juge et le Prophète, l'homme éclairé sur l'avenir, et l'ancien.
3 balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
Le cinquantenier, et l'homme d'autorité, le conseiller, et l'expert entre les artisans, et le bien-disant;
4 “Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
Et je leur donnerai de jeunes gens pour gouverneurs, et des enfants domineront sur eux.
5 Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
Et le peuple sera rançonné l'un par l'autre, et chacun par son prochain. L'enfant se portera arrogamment contre le vieillard, et l'homme abject contre l'honorable.
6 Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
Même un homme prendra son frère de la maison de son père, [et lui dira]; tu as un manteau, sois notre conducteur, et que cette dissipation-ci [soit] sous ta conduite.
7 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
[Et celui-là] lèvera [la main] en ce jour-là, en disant; je ne saurais y remédier, et en ma maison il n'y a ni pain ni manteau; ne me faites point donc conducteur du peuple.
8 Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
Certes Jérusalem est renversée, et Juda est tombé; parce que leur langue et leurs actions sont contre l'Eternel, pour irriter les yeux de sa gloire.
9 Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
Ce qu'ils montrent sur leur visage rend témoignage contr'eux, ils ont publié leur péché comme Sodome, et ne l'ont point célé; malheur à leur âme, car ils ont attiré le mal sur eux!
10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
Dites au juste, que bien lui sera: car [les justes] mangeront le fruit de leurs œuvres.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
Malheur au méchant [qui ne cherche qu'à faire] mal; car la rétribution de ses mains lui sera faite.
12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
Quant à mon peuple, les enfants sont ses prévôts, et les femmes dominent sur lui. Mon peuple, ceux qui te guident, [te] font égarer, et t'ont fait perdre la route de tes chemins.
13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
L'Eternel se présente pour plaider, il se tient debout pour juger les peuples.
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
L'Eternel entrera en jugement avec les Anciens de son peuple, et avec ses Principaux; car vous avez consumé la vigne, et ce que vous avez ravi à l'affligé est dans vos maisons.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Que vous revient-il de fouler mon peuple, et d'écraser le visage des affligés? dit le Seigneur, l'Eternel des armées.
16 Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
L'Eternel a dit aussi; parce que les filles de Sion se sont élevées, et ont marché la gorge découverte, et faisant signe des yeux, et qu'elles ont marché avec une fière démarche faisant du bruit avec leurs pieds,
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
L'Eternel rendra chauve le sommet de la tête des filles de Sion, et l'Eternel découvrira leur nudité.
18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
En ce temps-là le Seigneur ôtera l'ornement des sonnettes, et les agrafes, et les boucles;
19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
Les petites boîtes, et les chaînettes, et les papillotes;
20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
Les atours, et les jarretières, et les rubans, et les bagues à senteur, et les oreillettes;
21 òrùka ọwọ́ àti ti imú,
Les anneaux, et les bagues qui leur pendent sur le nez;
22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
Les mantelets, et les capes, et les voiles, et les poinçons,
23 dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
Et les miroirs, et les crêpes, et les tiares, et les couvre-chefs.
24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
Et il arrivera qu'au lieu de senteurs aromatiques, il y aura de la puanteur; et au lieu d'être ceintes, elles seront découvertes, et au lieu de cheveux frisés, elles auront la tête chauve; et au lieu de ceintures de cordon, [elles seront ceintes] de cordes de sac; et au lieu d'un beau teint, elles auront le teint tout hâlé.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
Tes gens tomberont par l'épée, et ta force par la guerre.
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.
Et ses portes se plaindront, et mèneront deuil; et elle sera vidée, et gisante par terre.

< Isaiah 3 >