< Isaiah 3 >
1 Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
The Commander of the armies of angels is about to take away from Jerusalem and [other places in] Judea everything that you depend on— all your food and water.
2 Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
He will take away your heroes and your [other] soldiers, your judges and your prophets, people who do rituals to find out what will happen in the future and the elders,
3 balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
army officers and [other] officials, advisors and skilled craftsmen and those who perform rituals to predict the future.
4 “Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
He will appoint boys to be your leaders; your children will rule you.
5 Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
People will treat each other cruelly: people will fight against their neighbors. Young people will insult older people, and vulgar/dishonorable people will sneer at people who should be honored.
6 Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
At that time, someone will grab one of his brothers in his father’s house and say to him, “You have a coat, [which shows that you are respected]. [So] you be our leader! You rule this [city, which is now] a pile of ruins!”
7 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
[But] his brother will reply, “[No], I cannot help you, [because] I do not have [any extra] food or clothes in this house. [So] do not appoint me to be your leader!”
8 Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
Jerusalem and [the other towns in] Judah will be destroyed, because [everything] that the people do and say there opposes Yahweh, who is powerful and glorious, and they refuse to obey him. They rebel against him.
9 Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
They even show on their faces that [they oppose Yahweh]. They are proud of their sins, like [the people of] Sodom were [long ago]; they do not try to hide their sins. [Because of their sins], terrible things will happen to them, [but] they will bring those disasters on themselves.
10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
[Yahweh told me to] tell the righteous people that good things will happen to them; they will enjoy the blessings that they will receive for their good deeds.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
[But] terrible things will happen to wicked people; they will be (paid back/punished) for [the evil things that] [MTY] they have done.
12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
[Now], youths [who have become leaders] treat my people cruelly, and women rule over my people. My people, your leaders are misleading you; they are causing you to go down the wrong road [MET].
13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
[It is as though] Yahweh has sat in his place in a courtroom and is ready to judge his people.
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
He will stand up to declare why the elders and rulers of his people should be punished: [he says], “The people of Israel are [like] [MET] a vineyard that I planted, but you have ruined it! Your houses are full of things that you have stolen from poor people.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
You should stop [RHQ] crushing my people! [It is as though] you are pushing the faces of poor people into the dirt!” [That is what] the Commander of the armies of angels says.
16 Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
Yahweh says this: “The women of Jerusalem are haughty/proud; they walk around sticking their chins out, and flirting [with men] with their eyes. They walk with tiny steps with bracelets on their ankles that jingle.
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
So I, Yahweh, will cause sores to be on their heads, and I will cause those beautiful women in Jerusalem to become bald.”
18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
At the time [that Yahweh does that], he will strip away everything that the women of Jerusalem wear to make themselves beautiful—the ornaments on their ankles and their headbands, their crescent necklaces,
19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
their earrings and bracelets and veils,
20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
their scarves and ankle bracelets and sashes, their perfumes and (charms/little things that they wear thinking that those things will protect them from evil),
21 òrùka ọwọ́ àti ti imú,
their signet rings and nose rings,
22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
their nice robes and capes and cloaks and purses,
23 dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
their mirrors and nice linen clothes and shawls.
24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
Instead of their having a nice smell from perfume, they will stink; instead of nice sashes, they will have ropes [around their waists because they will be captives]. Instead of having fancy hairdos, they will be bald. Instead of fancy/beautiful robes, they will wear rough sackcloth, and instead of being beautiful, they will be branded.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
Their husbands will be killed by [their enemies’] swords, and their soldiers [will also die] in battles.
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.
People [PRS] will mourn and cry at the gates [of the city]. The city will [be like] [MET] a woman who sits on the ground because everything that she owned is gone.