< Isaiah 29 >
1 Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli, ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí! Fi ọdún kún ọdún sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
Asi pay ti Ariel, Ariel, ti siudad a nagkampoan ni David! Kada tawen; agrambakkayo kadagiti fiesta.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún, òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
Ngem lakkubekto ti Ariel, ket agladingit ken agdung-awto daytoy; ket agbalinto daytoy kaniak a kas iti Ariel.
3 Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo, Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká, Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
Agkampoakto iti aglawlawyo ket lakubenkayonto babaen kadagiti nangangato nga alad a naaramid iti natiradan a kayo, ken pangatoekto dagiti aramatek a panglakubko kadakayo.
4 Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá; ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀. Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá, láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.
Maipababakayonto ken agsaokayonto manipud iti daga; agtaudto iti tapok ti saoyo. Kaslanto timek ti al-allia manipud iti uneg ti daga ti timekyo, ket nakapsutto unay ti saoyo manipud iti tapok.
5 Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná, agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù. Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
Ti bunggoy dagiti mangraraut kadakayo ket kaslanto napino a tapok, ken kaslanto taep a maiyangin dagiti adu a naulpit a tattao. Mapasamakto daytoy a saan a mapakpakadaan, iti apagdarikmat.
6 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá pẹ̀lú àrá àti ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá, àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun.
Dusaennakayonto ni Yahweh a Mannakabalin-amin babaen iti gurruod, ginggined, napigsa a tagari, napigsa nga angin ken naranggas a bagyo, ken gil-ayab ti makauram nga apuy.
7 Lẹ́yìn náà, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà, tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀ tí ó sì dó tì í, yóò dàbí ẹni pé nínú àlá, bí ìran ní òru
Maiyarigto daytoy iti maysa a tagtagainep, maysa a sirmata iti rabii: Ti bunggoy dagiti amin a nasion ket makirangetto iti Ariel ken iti sarikedked daytoy. Rautendanto daytoy ken dagiti pagsamsammakedan daytoy tapno maimameg daytoy.
8 àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun, ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀; tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi, ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá òkè Sioni jà.
Maiyarigto daytoy iti maysa a mabisin a tao nga agtagtagainep a mangmangan, ngem no makariing ket awan karga ti buksitna. Maiyarigto daytoy iti maysa a mawaw a tao nga agtagtagainep nga umin-inum, ngem no makariing ket matalimudaw isuna ken saan a maep-ep ti pannakawawna. Wen, ket kastanto ti kaiyarigan ti bunggoy dagiti nasion a mangraut iti Bantay Sion.
9 Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín, ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran; ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì, ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
Pagsiddaawenyo dagiti bagbagiyo ket agsiddaawkayo; pagbulsekenyo dagiti bagbagiyo ket agbulsekkayo! Agbartekkayo, ngem saan a babaen iti arak; agdiwerdiwerkayo ngem saan a gapu iti arak.
10 Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín: ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì; ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.
Ta imbukbok ni Yahweh kadakayo ti espiritu ti pannakarnek iti turog. Pinagkidemna dagiti matayo, dakayo a profeta, ken inabbunganna dagiti uloyo, dakayo a makakitkita iti masakbayan.
11 Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”
Dagiti amin a paltiing ket nagbalin kadakayo a kas kadagiti sasao iti libro a naselioan, a mabalin nga ited ti maysa a tao iti nakaadal, a kunana, “Basaem daytoy.” Kunana met, “Saanko a mabasa ta naselioan daytoy.”
12 Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”
No maited ti libro iti tao a saan a makabasa, kunana, “Basaem daytoy,” ibagana, “Saanak a makabasa.”
13 Olúwa wí pé: “Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn, wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi. Ìsìn wọn si mi ni a gbé ka orí òfin tí àwọn ọkùnrin kọ́ ni.
Kinuna ti Apo, “Umas-asideg kaniak dagitoy a tattao babaen kadagiti ngiwatda ken daydayawendak babaen kadagiti bibigda, ngem adayo kaniak dagiti pusoda. Ti panangdaydayawda kaniak ket bilin nga insuro dagiti tattao.
14 Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu; ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé, ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
Ngarud, kitaenyo, ituloykonto ti mangaramid iti nakaskasdaaw a banag kadagitoy a tattao, agsasaruno a nakakaskasdaaw. Agpukawto ti kinasirib dagiti masirib a tattaoda, ken mapukawto ti pannakaawat dagiti nanakman a tattaoda.”
15 Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa, tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn tí wọ́n sì rò pé, “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
Asi pay dagiti nainget a mangilemmeng kadagiti panggepda kenni Yahweh, ken dagiti adda iti kinasipnget ti aramidda. Kunada, “Siasino koma ngay ti makakitkita kadatayo, ken makaam-ammo kadatayo?
16 Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀, bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀! Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé, “Òun kọ́ ló ṣe mí”? Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé, “Kò mọ nǹkan”?
Binallikogyo dagiti banbanag! Mabalin kadi a maibilang a pitak ti agdamdamili, tapno ti banag a naaramid ket maibagana maipapan iti nangaramid kenkuana a, “Saannak nga inaramid,” wenno ti banag a nasukog ket ibagana maipapan iti nangsukog kenkuana a, “Saan isuna a makaawat?”
17 Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́ a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
Iti mabiit laeng a panawen, agbalinto a talon ti Lebanon, ken agbalinto a kabakiran ti talon.
18 Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà, láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
Iti dayta nga aldaw mangngegto ti tuleng dagiti sasao ti maysa a libro, ken makakitanto dagiti mata ti bulsek manipud iti nakaro a sipnget.
19 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa: àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Agrag-onto manen kenni Yahweh dagiti naidadanes, ken agrag-onto iti Nasantoan ti Israel dagiti nakurapay a tattao.
20 Aláìláàánú yóò pòórá, àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì, gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
Ta agsardengto dagiti naulpit, ken agpukawto ti managuyaw. Dagiti amin a mangay-ayat nga agaramid iti dakes ket mapukawto,
21 àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi, ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́ tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.
dagiti tattao a ti saoda ket pagbalinenna a nakabasol ti maysa a tao. Mangipakatda iti silo para kadagiti mangbirbirok iti hustisia iti ruangan ken imamegda dagiti nalinteg babaen iti panagulbodda.
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu: “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́; ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
Ngarud, daytoy ti kuna ni Yahweh maipapan iti balay ni Jacob— ni Yahweh, a nangsubbot kenni Abraham, “Saanton nga agbain ni Jacob, wenno agpusyaw ti rupana.
23 Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn, àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi, wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́, wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
Ngem inton makitana dagiti annakna, ti aramid dagiti imak, pagbalinendanto a nasantoan ti naganko. Pagbalinendanto a nasantoan ti nagan ti Nasantoan ni Jacob ken agbutengdanto iti Dios ti Israel.
24 Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀; gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”
Dagiti agbiddut iti naespirituan ket magun-oddanto ti pannakaawat, ken makasursuronto dagiti managriri.”