< Isaiah 29 >

1 Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli, ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí! Fi ọdún kún ọdún sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
Malheur à Ariel, à Ariel, la ville où David s'est campé; ajoutez année sur année, qu'on égorge des victimes pour les Fêtes.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún, òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
Mais je mettrai Ariel à l'étroit, et [la ville] ne sera que tristesse et que deuil, et elle me sera comme Ariel.
3 Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo, Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká, Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
Car je me camperai en rond contre toi, et je t'assiégerai avec des tours, et je dresserai contre toi des forts.
4 Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá; ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀. Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá, láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.
Et tu seras abaissée, et tu parleras [comme] de dedans la terre, et ta parole sera basse, [comme si elle sortait] de la poussière, et ta voix, comme [celle] d'un esprit de Python, sortira de la terre, et ta parole marmottera [comme si elle sortait] de la poussière.
5 Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná, agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù. Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
Et la multitude de tes étrangers sera comme de la poudre menue; et la multitude des terribles sera comme de la balle qui passe, et cela sera pour un petit moment.
6 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá pẹ̀lú àrá àti ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá, àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun.
Elle sera visitée par l'Eternel des armées avec des tonnerres, et avec des tremblements de terre, et avec un grand bruit, tempête, tourbillon, et flamme de feu dévorant.
7 Lẹ́yìn náà, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà, tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀ tí ó sì dó tì í, yóò dàbí ẹni pé nínú àlá, bí ìran ní òru
Et la multitude de toutes les nations qui feront la guerre à Ariel, et tous ceux qui combattront contre la [ville], et ceux qui la serreront de près, seront comme un songe d'une vision de nuit.
8 àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun, ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀; tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi, ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá òkè Sioni jà.
Et il arrivera, que comme celui qui a faim, songe qu'il mange, mais quand il est réveillé, son âme est vide; et comme celui qui a soif, songe qu'il boit, mais quand il est réveillé, il est las, et son âme est altérée, ainsi sera la multitude de toutes les nations qui combattront contre la montagne de Sion.
9 Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín, ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran; ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì, ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
Arrêtez-vous, et vous étonnez; écriez-vous, et criez; Ils se sont enivrés, mais non pas de vin; ils chancellent, mais non pas à cause de la cervoise.
10 Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín: ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì; ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.
Car l'Eternel a répandu sur vous un esprit d'un profond dormir; il a bouché vos yeux; il a bandé [ceux de] vos Prophètes, et de vos principaux Voyants.
11 Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”
Et toute vision vous sera comme les paroles d'un livre cacheté qu'on donnerait à un homme de lettres en [lui] disant; Nous te prions, lis ceci; et il répondrait: Je ne saurais, car il est cacheté.
12 Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”
Puis si on le donnait à quelqu'un qui ne fût point homme de lettres, en lui disant; nous te prions, lis ceci; il répondrait; je ne sais point lire.
13 Olúwa wí pé: “Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn, wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi. Ìsìn wọn si mi ni a gbé ka orí òfin tí àwọn ọkùnrin kọ́ ni.
C'est pourquoi le Seigneur dit; parce que ce peuple s'approche de moi de sa bouche, et qu'ils m'honorent de leurs lèvres, mais qu'il a éloigné son cœur de moi, et parce que la crainte qu'ils ont de moi est un commandement d'hommes, enseigné [par des hommes];
14 Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu; ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé, ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
A cause de cela, voici, je continuerai de faire à l'égard de ce peuple-ci des merveilles et des prodiges étranges: c'est que la sapience de ses sages périra, et l'intelligence de ses hommes savants disparaîtra.
15 Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa, tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn tí wọ́n sì rò pé, “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
Malheur à ceux qui veulent aller plus loin que l'Eternel, pour cacher leur conseil, et dont les œuvres sont dans les ténèbres, et qui disent; qui nous voit, et qui nous aperçoit?
16 Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀, bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀! Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé, “Òun kọ́ ló ṣe mí”? Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé, “Kò mọ nǹkan”?
Ce que vous renversez ne sera-t-il pas réputé comme l'argile d'un potier? même, l'ouvrage dira-t-il de celui qui l'a fait: il ne m'a point fait? et la chose formée dira-t-elle de celui qui l'a formée; il n'y entendait rien?
17 Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́ a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
Le Liban ne sera-t-il pas encore dans très-peu de temps changé en un Carmel? et Carmel ne sera-t-il pas réputé comme une forêt?
18 Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà, láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
Et les sourds entendront en ce jour-là les paroles du livre, et les yeux des aveugles étant délivrés de l'obscurité et des ténèbres, verront.
19 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa: àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Et les débonnaires auront joie sur joie en l'Eternel, et les pauvres d'entre les hommes s'égayeront au Saint d'Israël.
20 Aláìláàánú yóò pòórá, àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì, gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
Car le terrible prendra fin, et le moqueur sera consumé, et tous ceux qui veillent pour commettre l'iniquité, seront retranchés.
21 àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi, ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́ tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.
Ceux qui font tenir pour coupables les hommes pour une parole, et qui tendent des pièges à celui qui les reprend en la porte, et qui font tomber le juste en confusion.
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu: “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́; ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
C'est pourquoi l'Eternel, qui a racheté Abraham, a dit ainsi touchant la maison de Jacob; Jacob ne sera plus honteux, et sa face ne pâlira plus.
23 Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn, àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi, wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́, wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
Car quand il verra ses fils être un ouvrage de mes mains au milieu de lui, ils sanctifieront mon Nom; ils sanctifieront, [dis-je], le Saint de Jacob, et redouteront le Dieu d'Israël.
24 Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀; gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”
Et ceux dont l'Esprit s'était fourvoyé deviendront prudents; et ceux qui murmuraient apprendront la doctrine.

< Isaiah 29 >