< Isaiah 29 >

1 Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli, ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí! Fi ọdún kún ọdún sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
Malheur à la ville d'Ariel, que David a combattue! Assemblez vos récoltes; encore une année, puis une année, ensuite vous mangerez, vous mangerez avec Moab.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún, òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
Car je briserai Ariel; sa force et sa richesse seront à moi.
3 Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo, Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká, Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
Et je t'investirai comme a fait David, et je t'entourerai de palissades, et j'élèverai des tours autour de toi.
4 Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá; ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀. Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá, láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.
Et tes paroles tomberont à terre; et tes paroles seront enfouies dans la terre; et ta voix sera comme celle des hommes qui la font sortir de terre, et tu n'auras qu'un filet de voix à rase terre.
5 Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná, agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù. Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
Mais la richesse des impies sera comme la poussière que soulèvent des roues, et la multitude de ceux qui t'oppriment, comme le duvet emporté par le vent. Et ce sera comme un moment insaisissable,
6 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá pẹ̀lú àrá àti ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá, àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun.
Soudain, venu du Seigneur Dieu des armées; car sa visite sera accompagnée de tonnerres, de tremblements de terre et de grands bruits; tourbillon impétueux, flamme dévorante.
7 Lẹ́yìn náà, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà, tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀ tí ó sì dó tì í, yóò dàbí ẹni pé nínú àlá, bí ìran ní òru
Et la richesse de toutes les nations qui auront attaqué Ariel, et tous ceux qui auront combattu Jérusalem, et tous ceux qui se seront réunis contre elle et l'auront opprimée seront comme le songe d'un homme qui s'éveille.
8 àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun, ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀; tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi, ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá òkè Sioni jà.
Comme ceux qui, dans le sommeil, boivent et mangent, et ils s'éveillent, et c'était un vain songe; comme un homme qui s'était endormi altéré rêve qu'il boit, et se réveille avec sa soif, voyant que son âme a espéré en vain: telle sera la richesse de tous les Gentils qui auront porté les armes contre la montagne de Sion.
9 Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín, ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran; ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì, ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
Soyez dans l'étonnement, soyez hors de vous, et chancelez d'ivresse, non à cause des boissons fermentées ou du vin;
10 Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín: ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì; ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.
Mais parce que le Seigneur vous a abreuvés d'un esprit de componction; et il vous fermera les yeux, et il aveuglera vos prophètes, vos princes et vos voyants, instruits des choses cachées.
11 Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”
Et toutes ces choses seront pour vous comme les paroles de ce livre scellé que l'on donne à un homme qui sait lire, en lui disant: Lis cela; et il dit: Je ne puis, car il est scellé.
12 Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”
Et on donne ce livre à un homme qui ne sait pas lire, en lui disant: Lis cela; et il dit: Je ne sais lire
13 Olúwa wí pé: “Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn, wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi. Ìsìn wọn si mi ni a gbé ka orí òfin tí àwọn ọkùnrin kọ́ ni.
Et le Seigneur a dit: Ce peuple s'approche de moi en parole, et il m'honore des lèvres; mais son cœur est loin de moi. Ils m'honorent en vain, enseignant la science et les maximes des hommes.
14 Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu; ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé, ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
A cause de cela, voilà que je vais encore transporter ce peuple; je les transporterai, et je perdrai la sagesse des sages, et je tromperai la prudence des prudents.
15 Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa, tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn tí wọ́n sì rò pé, “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
Malheur à ceux qui approfondissent leurs conseils, mais non avec le Seigneur! Malheur à ceux qui méditent en secret! ils feront leurs œuvres dans les ténèbres, et ils diront: Qui nous a vus? et qui saura ce que nous faisons?
16 Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀, bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀! Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé, “Òun kọ́ ló ṣe mí”? Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé, “Kò mọ nǹkan”?
Ne serez-vous pas comptés comme l'argile du potier? Est-ce que l'ouvrage dira à l'ouvrier: Tu ne m'as point façonné? Est-ce que l'œuvre dira à l'artisan: Tu ne m'as pas faite avec intelligence?
17 Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́ a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
Est-ce que dans peu de temps le Liban ne sera point changé comme le mont Carmel? Est-ce que le mont Carmel ne sera pas réputé une forêt?
18 Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà, láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
Et en ce jour les sourds entendront les paroles du livre, avec ceux qui sont dans les ténèbres et ceux qui sont dans les brouillards. Les yeux des aveugles verront;
19 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa: àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Et à cause du Seigneur les pauvres tressailliront d'allégresse, et les hommes désespérés seront rassasiés de joie.
20 Aláìláàánú yóò pòórá, àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì, gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
L'injuste n'est plus, le superbe a péri; ceux qui méchamment s'écartaient de la loi ont été exterminés;
21 àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi, ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́ tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.
Ainsi que ceux qui, par leurs discours, entraînaient les hommes à pécher; et on tiendra à scandale tous ceux qui tendaient des pièges aux portes de la ville, parce qu'ils auront conduit le juste dans l'injustice.
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu: “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́; ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
A cause de cela, voici ce que dit le Seigneur sur la maison de Jacob, qu'il avait retranchée d'Abraham: Jacob ne sera plus confondu, il ne changera plus de visage.
23 Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn, àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi, wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́, wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
Mais lorsque mes enfants auront vu mes œuvres, pour l'amour de moi, ils sanctifieront le Saint de Jacob, et ils craindront le Dieu d'Israël.
24 Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀; gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”
Et ceux qui, en leur esprit, se sont égarés, connaîtront la vraie science; ceux qui murmurent apprendront à obéir; et les langues qui bégayent sauront dire des paroles de paix.

< Isaiah 29 >