< Isaiah 28 >

1 Ègbé ni fún adé ìgbéraga, fún àwọn ọ̀mùtí Efraimu, àti fún ìtànná rírọ, ẹwà ògo rẹ̀, tí ó tò sí orí àfonífojì ẹlẹ́tù lójú àti sí ìlú náà ìgbéraga àwọn tí ọtí wáìnì ń pa tí a rẹ̀ sílẹ̀.
Biada koronie pychy, pijakom Efraima, których wspaniała ozdoba jest więdnącym kwiatem rosnącym na szczycie urodzajnych dolin odurzonych winem!
2 Kíyèsi i, Olúwa ní ẹnìkan tí ó le, tí ó sì lágbára, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ yìnyín àti bí ìjì apanirun, gẹ́gẹ́ bí àrọ̀dá òjò àti òjò tí ó mú ìkún omi wá, òun yóò fi tipátipá sọ ọ́ sílẹ̀.
Oto ktoś od Pana, mocny i silny, jak burza gradowa, jak niszcząca nawałnica, jak ulewa gwałtownych rwących wód, rzuci [ją] na ziemię swoją ręką.
3 Adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí Efraimu, ni a ó fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Zostanie zdeptana nogami korona pychy, pijacy Efraima.
4 Òdòdó tí ó ń rọ náà tí í ṣe ẹwà ògo rẹ̀, tí ó tò sí orí àfonífojì ẹlẹ́tù lójú, yóò dàbí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó pọ́n ṣáájú ìkórè bí ẹnikẹ́ni bá ti rí i tí ó sì mú un ní ọwọ́ rẹ̀, òun a sì mì ín.
A wspaniała ozdoba, która jest na szczycie urodzajnej doliny, będzie więdnącym kwiatem jak przed latem wczesny owoc; kto go tylko zobaczy, weźmie do ręki i zje.
5 Ní ọjọ́ náà Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ́ adé tí ó lógo, àti adé tí ó lẹ́wà fún àwọn ènìyàn rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù.
W tym dniu PAN zastępów będzie koroną chwały i diademem ozdoby dla resztki swojego ludu;
6 Òun yóò sì jẹ́ ẹ̀mí ìdájọ́ òdodo fún ẹni tí ó jókòó ní ìtẹ́ ìdájọ́ àti orísun agbára fún àwọn ẹni tí ó ń dá ogun padà ní ẹnu ibodè.
Duchem sądu dla zasiadającego w sądzie i mocą dla tych, którzy odpierają atak aż do bramy.
7 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n fún ọtí wáìnì wọ́n pòòrì fún ọtí líle, àwọn àlùfáà àti wòlíì ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n fún ọtí líle wọ́n ta gíẹ́ gíẹ́ fún ọtí wáìnì wọ́n ń lọ́ bìrì bìrì fún ọtí líle, wọ́n ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nígbà tí wọ́n ń ríran, wọ́n kọsẹ̀ nígbà tí wọ́n ń mú ìpinnu wá.
Ale również ci od wina błądzą i od mocnego napoju zataczają się. Kapłan i prorok błądzą od mocnego napoju, utonęli w winie, zataczają się od mocnego napoju, błądzą w widzeniach, potykają się w sądzie.
8 Gbogbo orí tábìlì ni ó kún fún èébì kò sì ṣí ibìkan tí kò sí ẹ̀gbin.
Wszystkie ich stoły bowiem są pełne wymiotów i plugastwa, tak że nie ma [czystego] miejsca.
9 “Ta ni ẹni náà tí ó ń gbìyànjú àti kọ́? Ta ni ó sì ń ṣàlàyé ìròyìn in rẹ̀ fún? Sí àwọn ọmọdé tí a já lẹ́nu ọmú wọn, sí àwọn tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gbà lẹ́nu ọmú.
Kogo ma uczyć poznania? Komu ma wyjaśnić naukę? Czyż odstawionym od mleka i odłożonym od piersi?
10 Nítorí tí í ṣe: báyìí ni orí, ṣe, kí o si túnṣe, ṣe kí o si túnṣe, àṣẹ n gorí àṣẹ, àṣẹ n gorí àṣẹ; díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn.”
Ponieważ podaje się przykazanie za przykazaniem, przykazanie za przykazaniem, przepis za przepisem, przepis za przepisem, trochę tu, trochę tam.
11 Ó dára báyìí, pẹ̀lú ètè àjèjì àti ahọ́n àìmọ̀ Ọlọ́run yóò bá àwọn ènìyàn yìí sọ̀rọ̀
Bo wargami jąkających się i obcym językiem będę mówił do tego ludu.
12 àwọn tí ó sọ fún wí pé, “Èyí ni ibi ìsinmi, jẹ́ kí àwọn aláàárẹ̀ sinmi”; àti pé, “Èyí ni ibi ìsinmi”; ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sílẹ̀.
A gdy im powiedział: To jest odpoczynek, dajcie odpocząć spracowanemu; to jest wytchnienie. Ale oni nie chcieli słuchać.
13 Fún ìdí èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa sí wọn yóò di pé, ṣe èyí, ṣe ìyẹn, àṣẹ n gorí àṣẹ, àṣẹ n gorí àṣẹ; díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò lọ tí wọn yóò tún ṣubú sẹ́yìn, wọn yóò fi ara pa, wọn yóò bọ́ sínú okùn a ó sì gbá wọn mú.
I słowo PANA będzie im: przykazanie za przykazaniem, przykazanie za przykazaniem, przepis za przepisem, przepis za przepisem, trochę tu, trochę tam, po to, aby szli, padli na wznak i rozbili się, aby zostali uwikłani i pojmani.
14 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn, tí ń jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní Jerusalẹmu.
Dlatego słuchajcie słowa PANA, wy, mężowie szyderczy, panujący nad tym ludem, który jest w Jerozolimie.
15 Ẹ fọ́n pé, “Àwa ti bá ikú mulẹ̀, pẹ̀lú ibojì ni àwa ti jọ ṣe àdéhùn. Nígbà tí ìbáwí gbígbóná fẹ́ kọjá, kò le kàn wá lára, nítorí a ti fi irọ́ ṣe ààbò o wa àti àìṣòótọ́ ibi ìpamọ́ wa.” (Sheol h7585)
Ponieważ mówicie: Zawarliśmy przymierze ze śmiercią i z piekłem mamy układ; gdy przejdzie bicz gwałtowny, nie dosięgnie nas, gdyż kłamstwo uczyniliśmy naszą ucieczką i skryliśmy się za fałszem; (Sheol h7585)
16 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Kíyèsi i, èmi gbé òkúta kan lélẹ̀ ní Sioni, òkúta tí a dánwò, òkúta igun ilé iyebíye fún ìpìlẹ̀ tí ó dájú; ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé kì yóò ní ìfòyà.
Dlatego tak powiedział Pan BÓG: Oto kładę jako grunt na Syjonie kamień, kamień wypróbowany, węgielny, drogocenny, utwierdzony fundament. Kto uwierzy, nie pospieszy się.
17 Èmi yóò fi ìdájọ́ ṣe okùn òsùwọ̀n àti òdodo òjé òsùwọ̀n; yìnyín yóò gbá ààbò yín dànù àti irọ́, omi yóò sì kún bo gbogbo ibi tí ẹ ń fi ara pamọ́ sí mọ́lẹ̀.
A wykonam sąd według sznura, a sprawiedliwość według pionu. I grad zmiecie schronienie kłamstw, a wody zaleją kryjówkę.
18 Májẹ̀mú yín tí ẹ bá ikú dá ni a ó fa igi lé; àdéhùn yín pẹ̀lú ibojì ni kì yóò dúró. Nígbà tí ìbínú gbígbóná náà bá fẹ́ kọjá, a ó ti ipa rẹ̀ lù yín bolẹ̀. (Sheol h7585)
Wasze przymierze ze śmiercią zostanie zerwane, a wasz układ z piekłem nie ostoi się; gdy ten bicz gwałtowny przejdzie, zostaniecie przez niego zdeptani. (Sheol h7585)
19 Nígbàkígbà tí ó bá ti wá ni yóò máa gbé ọ lọ, ni àràárọ̀, ní ọ̀sán àti ní òru, ni yóò máa fẹ́ kọjá lọ.” Ìmòye ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yìí yóò máa mú ìpayà ńlá wá.
Jak tylko zacznie przechodzić, pochwyci was, bo każdego poranka będzie przechodzić, dniem i nocą. Sam tylko postrach zaprowadzi was do zrozumienia tego, co słyszeliście;
20 Ibùsùn kúrú púpọ̀ fún ìnara lé lórí, ìbora kò fẹ̀ tó láti yí ara yín ká.
Bo łóżko będzie za krótkie, aby się na nim rozciągnąć, przykrycie zbyt wąskie, by się nim owinąć.
21 Olúwa yóò dìde sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní òkè Perasimu yóò ru ara rẹ̀ sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní àfonífojì Gibeoni— láti ṣe iṣẹ́ rẹ̀, abàmì iṣẹ́ ẹ rẹ̀, yóò ṣe iṣẹ́ rẹ̀, àní àjèjì iṣẹ́ rẹ̀.
PAN bowiem powstanie jak na górze Perazym i rozgniewa się jak w dolinie Gibeon, aby dokonać swego dzieła, swego niezwykłego dzieła, aby dokończyć swoje zadanie, swoje niezwykłe zadanie.
22 Ní ìsinsin yìí ẹ dákẹ́ ẹlẹ́yà ṣíṣe, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìdè e yín yóò le sí i; Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ fún mi nípa àṣẹ ìparun ti ó ti pa lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
Teraz więc nie naśmiewajcie się, aby wasze węzły nie zacisnęły się mocniej, gdyż słyszałem od Pana, BOGA zastępów, że postanowione jest zniszczenie na całej ziemi.
23 Tẹ́tí kí o sì gbọ́ ohùn mi, fi ara balẹ̀ kí o sì gbọ́ ohun tí mo sọ.
Nadstawcie uszu, posłuchajcie mego głosu; bądźcie uważni, słuchajcie mojej mowy.
24 Nígbà tí àgbẹ̀ kan bá tu ilẹ̀ láti gbìn yóò ha máa tulẹ̀ títí bi? Ǹjẹ́ yóò ha máa tu ilẹ̀ kí ó sì máa jọ̀ ọ́ títí lọ bí?
Czyż oracz codziennie orze, aby siać? [Czy] robi bruzdy i bronuje swoją rolę?
25 Nígbà tí òun bá ti tẹ́ ojú ilẹ̀ rẹ̀ pẹrẹsẹ òun kò ha ń fúnrúgbìn dílì kí ó sì fúnrúgbìn kummini ká? Kí ó sì gbin alikama lẹ́sẹẹsẹ, barle tí a yàn, àti spelti ní ipò rẹ̀?
Czyż gdy wyrówna jej powierzchnię, nie rozsiewa czarnuszki, nie rozsiewa kminu i nie obsiewa pszenicą wyborną, jęczmieniem przednim i orkiszem w odpowiednich miejscach?
26 Ọlọ́run rẹ̀ tọ́ ọ ṣọ́nà ó sì kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ ní ọ̀nà tó tọ́.
Jego Bóg uczy go roztropności i poucza go.
27 Nítorí a kò fi ohun èlò ìpakà dili, bẹ́ẹ̀ ni a kì í yí kẹ̀kẹ́ ẹrù kiri lórí kummini; ṣùgbọ́n ọ̀pá ni a fi ń pa dili jáde, ọ̀gọ ni a sì lu kummini.
Czarnuszki bowiem nie młóci się saniami młockarskimi ani nie przetacza się koła wozu po kminku; ale kijem wybija się czarnuszkę, a kminek – laską.
28 A gbọdọ̀ lọ ìyẹ̀fun kí a tó ṣe àkàrà; bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì í máa pa á lọ títí láé. Bí ó tilẹ̀ yí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ìpakà a rẹ̀ lórí i rẹ̀, àwọn ẹṣin rẹ̀ kò le lọ̀ ọ́.
Pszenicę młóci się, ale nie bez końca, i nie pociera jej kołem wozu ani jej nie kruszy zaprzęgiem.
29 Gbogbo èyí pẹ̀lú ti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, oníyanu ní ìmọ̀ràn àti ológo ní ọgbọ́n.
I to także pochodzi od PANA zastępów, który jest cudowny w radzie i wielki w działaniu.

< Isaiah 28 >