< Isaiah 27 >

1 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
På den tiden skall HERREN med sitt svärd, det hårda, det stora och starka, hemsöka Leviatan, den snabba ormen, och Leviatan, den ringlande ormen, och skall dräpa draken, som ligger i havet.
2 Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
På den tiden skall finnas en vingård, rik på vin, och man skall sjunga om den:
3 Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
Jag, HERREN, är dess vaktar, åter och åter vattnar jag den. För att ingen skall skada den, vaktar jag den natt och dag.
4 Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
Jag vredgas icke på den; nej, om tistel och törne ville begynna strid, så skulle jag gå löst därpå och bränna upp alltsammans.
5 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
Eller ock måste man söka skydd hos mig och göra fred med mig; ja, fred måste man göra med mig.
6 Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
I tider som komma skall Jakob skjuta rötter och Israel grönska och blomstra; jordkretsen skola de uppfylla med sin frukt.
7 Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
Har man väl plågat dem så, som han plågade deras plågare? Eller dräptes de så, som deras dräpta fiender blevo dräpta?
8 Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
Nej, väl näpste han folket, när han förkastade och försköt det, väl ryckte han bort det med sin hårda vind, på östanstormens dag;
9 Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
men därför kan ock Jakobs missgärning då bliva försonad och deras synds borttagande då giva fullmogen frukt, när alla stenar i deras altaren äro förstörda -- såsom då man krossar sönder kalkstycken -- och när Aseror och solstoder ej mer resas upp.
10 Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
Se, den fasta staden ligger öde, den har blivit en folktom plats, övergiven såsom en öken, kalvar gå där i bet och lägra sig där och avbita de kvistar där finnas.
11 Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
Och när grenarna äro torra, bryter man av dem, och kvinnor komma och göra upp eld med dem. Ty detta är icke ett folk med förstånd; därför visar deras skapare dem intet förbarmande, och deras danare dem ingen misskund.
12 Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
Och det skall ske på den tiden att HERREN anställer en inbärgning, från den strida floden intill Egyptens bäck; och I skolen varda insamlade, en och en, I Israels barn.
13 Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.
Och det skall ske på den tiden att man stöter i en stor basun; och de som hava varit borttappade i Assyriens land och fördrivna till Egyptens land, de skola då komma; och de skola tillbedja HERREN på det heliga berget i Jerusalem.

< Isaiah 27 >