< Isaiah 27 >
1 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
Dnia onego nawiedzi Pan mieczem swoim srogim, wielkim i mocnym, Lewiatana, węża długiego, i Lewiatana, węża skręconego, a zabije smoka, który jest w morzu.
2 Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
Dnia onego śpiewajcie o winnicy wybornego wina.
3 Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
Ja Pan, który jej strzegę, co chwilka odwilżać ją będę, a żeby jej kto nie psuł, w nocy i we dnie strzedz jej będę.
4 Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
Zapalczywości żadnej we mnie niemasz. Któż mi da oset albo ciernie, abym przeciwko niej walczył, i spalił ją do szczętu?
5 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
Izali kto ujmie siłę moję, aby uczynił pokój zemną? aby pokój, mówię, uczynił zemną?
6 Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
Przyjdzie do tego, że się Jakób rozkorzeni, zakwitnie i rozrodzi się Izrael, i napełni okrąg ziemski owocem.
7 Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
Bo izali go tak uderzy, jako uderzył nieprzyjaciela jego? albo izali go zamordował, jako inni są zamordowani od niego?
8 Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
Owszem, miernie go karał, i w ten czas, gdy go wypychał i gdy go nieprzyjaciel wiatrem swoim gwałtownym w dzień wschodniego wiatru, zabierał.
9 Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
Przetoż tym sposobem oczyszczona będzie nieprawość Jakóbowa; a tenci jest wszystek pożytek, że odejmie grzech jego, gdy rozrzuci wszystkie kamienie ołtarza, jako kamienie wapienne rozszarpane, a nie ostoją się gaje i obrazy słoneczne.
10 Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
Gdy miasto obronne spustoszeje, a będzie mieszkaniem porzuconem i spustoszonem jako pustynia. Tam się paść, i tam legać będzie cielec, i ogryzie latorosłki jego.
11 Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
Gdy poschną gałązki jego, pokruszone będą, a niewiasty przyszedłszy zapalą je. Albowiem ten lud nie ma żadnego rozumu; przetoż nie zmiłuje się nad nim, który go uczynił, a który go stworzył, nie zlituje się nad nim.
12 Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
Dnia onego, gdy się Pan będzie mścił od łożyska rzeki aż do potoku Egipskiego, wy synowie Izraelscy po jednemu zebrani będziecie.
13 Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.
Stanie się też dnia onego, że zatrąbią w trąbę wielką, i przyjdą, którzy byli poginęli w ziemi Assyryjskiej, i którzy byli zagnani do ziemi Egipskiej; i będą się Panu kłaniali na górze świętej w Jeruzalemie.