< Isaiah 27 >

1 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
Ngalolosuku iNkosi ngenkemba yayo elukhuni lenkulu lelamandla izajezisa uLeviyathani, inyoka ebalekayo, ngitsho uLeviyathani inyoka egoqanayo, ibulale umgobho oselwandle.
2 Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
Ngalolosuku hlabelelani ngaso isivini sewayini elibomvu.
3 Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
Mina Nkosi, ngiyasilondoloza, ngiyasithelela isikhathi sonke; hlezi kube khona osonayo ngisilondoloze ebusuku lemini.
4 Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
Ukuthukuthela kakukho kimi. Ngubani ongabeka ukhula oluhlabayo lameva kumelane lami empini? Bengizamatsha ngidabule phakathi kwakho, ngikutshise kanyekanye.
5 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
Kumbe kabambelele emandleni ami, enze ukuthula lami; uzakwenza ukuthula lami.
6 Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
Izakwenza abavela koJakobe bagxile, uIsrayeli uzahluma, akhahlele, agcwalise ubuso bomhlaba ngezithelo.
7 Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
Imtshayile yini njengokutshaya kwayo oyitshayayo? Ubulewe yini njengokubulawa kwababuleweyo bakhe?
8 Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
Ngesilinganiso ekukuxotsheni izaphikisana lakho; izakususa ngomoya wayo olukhuni ngosuku lomoya wempumalanga.
9 Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
Ngakho ngalokhu isiphambeko sikaJakobe sizahlawulelwa; lalokhu kuyisithelo sonke sokususa isono sakhe, lapho esenza ukuthi wonke amatshe elathi abe njengamatshe ekalaga avuthuziweyo, izixuku lamalathi elanga kakuyikuma.
10 Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
Ngoba umuzi obiyelweyo uzakuba wodwa, indawo yokuhlala ixotshwe, itshiywe njengenkangala; lapho ithole lizakudla khona, lilale khona, liqede izingatsha zawo.
11 Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
Lapho ingatsha zawo sezomile zizakwephulwa; abesifazana beze bazibase; ngoba kabasibantu abaqedisisayo; ngakho-ke lowo owabenzayo kayikubahawukela, lowababumbayo kayikubatshengisa umusa.
12 Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
Kuzakuthi-ke ngalolosuku iNkosi ibhule kusukela esifudlaneni somfula kuze kube semfuleni weGibhithe; lina-ke lizabuthwa ngamunye ngamunye, bantwana bakoIsrayeli.
13 Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.
Kuzakuthi-ke ngalolosuku kuvuthelwe uphondo olukhulu, lalabo ababebhubhe elizweni leAsiriya labaxotshelwe elizweni leGibhithe, bazabuya bayikhonze iNkosi entabeni engcwele eJerusalema.

< Isaiah 27 >