< Isaiah 27 >

1 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
At that time, Yahweh will punish Leviathan, the swift-moving monster/dragon, that coiling serpent that lives in the sea. Yahweh will kill it with his sharp, huge, and powerful sword.
2 Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
At that time, [Yahweh will say], “You [Israeli people, who are like] [MET] a fruitful vineyard, must sing!
3 Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
I will [protect you] [like a farmer] [MET] waters his crops carefully [in order that they will grow well]. I will guard you day and night, in order that no one harms you.
4 Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
I am no [longer] angry [with my people]; [if any of your enemies try to injure you like briers and thorns injure people] [MET], I will attack them [in battles]; I will get rid of them completely,
5 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
unless they request me to protect them; I strongly invite them to make peace with me [DOU]!”
6 Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
There will be a time when the (descendants of Jacob/Israeli people) will [prosper like] a plant that has good roots; they will be like [MET] trees that bud and blossom and bear a lot of fruit; [what they do will bless] all the people in the world.
7 Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
[But now I ask], has Yahweh punished us Israelis like he punished our enemies? Has he punished us as much as he punished them?
8 Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
[No, he has not done that], [but] he punished us Israeli people and (exiled us/forced us to leave our country); we were taken away from our land as though [SIM] we were struck by a windstorm from the east.
9 Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
Yahweh did that in order to punish us for our sins, and remove our guilt. As a result [of our being exiled], all the altars to other gods [in Israel] will be demolished, and we will be forgiven for the sins that we have committed. There will be no more poles for worshiping the goddess Asherah, or altars for burning incense to other gods; they will all be torn down.
10 Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
The cities that have strong walls around them will be empty; like the desert, they will have no one living in them. The houses will be abandoned, and the streets will be full of weeds. Calves will eat grass there and lie down there; they will chew up all the leaves on the trees.
11 Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
[The Israeli people are like] [MET] dry branches on a tree; women break them off and use them to make fires [under their cooking pots]. Our Israeli people do not have any sense; so Yahweh, who created them, will not act mercifully toward them or be kind to them.
12 Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
[However], there will be a time when Yahweh will gather them together [again; he will separate them from the people who have conquered them, like people] separate wheat from chaff. He will bring them [back to Israel], one by one, from [the land between] the Euphrates River [in the northeast] and the brook at the border of Egypt [in the southwest].
13 Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.
At that time, a trumpet will be blown very loudly. And those who were exiled to Assyria and Egypt and who almost died there will return to Jerusalem, to worship Yahweh on [Zion], his holy hill.

< Isaiah 27 >