< Isaiah 26 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda. Àwa ní ìlú alágbára kan, Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe ògiri àti ààbò rẹ̀.
În acea zi se va cânta această cântare în ţara lui Iuda: Avem o cetate tare; salvare va rândui Dumnezeu pentru ziduri şi fortificaţii.
2 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé, orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
Deschideţi porţile, ca naţiunea cea dreaptă care ţine adevărul să intre.
3 Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin, nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Tu îl vei ţine în desăvârşită pace, pe cel a cărui minte este fixată asupra ta, pentru că el se încrede în tine.
4 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé, nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta ayérayé náà.
Încredeţi-vă în DOMNUL pentru totdeauna, fiindcă în DOMNUL IEHOVA este tărie veşnică,
5 Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀ ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀; ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Fiindcă el înjoseşte pe cei ce locuiesc în înălţime; cetatea îngâmfată o umileşte; o umileşte până la pământ; o aduce în ţărână.
6 Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ẹsẹ̀ aninilára n nì, ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.
Piciorul o va călca, picioarele săracilor şi paşii celor nevoiaşi.
7 Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú, ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà àwọn olódodo ṣe geere.
Calea celui drept este integritate; tu, cel mai integru, cântăreşti calea celui drept.
8 Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ àwa dúró dè ọ́; orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
Da, pe calea judecăţilor tale, Doamne, te-am aşteptat; dorinţa sufletului nostru este pentru numele tău şi pentru amintirea ta.
9 Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru; ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ. Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
Cu sufletul meu te-am dorit în noapte; da, cu duhul meu din mine te voi căuta devreme, deoarece când judecăţile tale sunt pe pământ, locuitorii lumii vor învăţa dreptatea.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà wọn kò kọ́ láti sọ òdodo; kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
Să fie arătată favoare celui stricat, totuşi el nu va învăţa dreptatea; în ţara integrităţii el se va purta nedrept şi nu va privi maiestatea DOMNULUI.
11 Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ṣùgbọ́n àwọn kò rí i. Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ kí ojú kí ó tì wọ́n; jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn ọ̀tá rẹ jó wọn run.
DOAMNE, când mâna ta se înalţă, ei nu vor vedea; ci vor vedea şi vor fi ruşinaţi de invidia lor faţă de popor; da, focul duşmanilor tăi îi va mistui.
12 Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa; ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni ó ṣe é fún wa.
DOAMNE, tu vei rândui pace pentru noi; căci de asemenea ai lucrat toate faptele noastre în noi.
13 Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí, ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
DOAMNE Dumnezeul nostru, alţi domni în afară de tine au avut stăpânire asupra noastră; dar numai prin tine vom aminti despre numele tău.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́; gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́. Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán, ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
Ei sunt morţi, nu vor trăi; sunt decedaţi, nu se vor mai ridica; de aceea tu i-ai cercetat şi i-ai nimicit şi ai făcut toată amintirea lor să piară.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa; ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i. Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ; ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.
Tu ai înmulţit naţiunea, O DOAMNE, ai înmulţit naţiunea, tu eşti glorificat, ai mutat-o departe până la toate marginile pământului.
16 Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn; nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn, wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
DOAMNE, în tulburare te-au cercetat, au turnat o rugăciune când pedeapsa ta a fost asupra lor.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
Ca o femeie însărcinată, care se apropie de timpul ei de a naşte, este în durere şi strigă în junghiurile ei, astfel am fost noi în ochii tăi, DOAMNE.
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora, ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ. Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé; àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.
Am fost însărcinaţi, am fost în durere şi parcă am fi născut vânt; nu am lucrat nicio eliberare pe pământ, nici nu au căzut locuitorii lumii.
19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè ara wọn yóò dìde. Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀, dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀. Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀, ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.
Morţii tăi vor trăi, împreună cu trupul meu mort se vor ridica ei. Treziţi-vă şi cântaţi, voi care locuiţi în ţărână; căci roua ta este ca roua ierburilor şi pământul va da afară pe cei morţi.
20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín, ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀ títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
Vino, poporul meu, intră în încăperile tale şi închide-ţi uşile după tine, ascunde-te ca pentru puţin timp, până când indignarea va fi trecut.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀ láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀; kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.
Fiindcă, iată, DOMNUL iese din locul său să pedepsească pe locuitorii pământului pentru nelegiuirea lor; pământul de asemenea îşi va arăta sângele şi nu va mai acoperi pe ucişii lui.

< Isaiah 26 >