< Isaiah 26 >
1 Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda. Àwa ní ìlú alágbára kan, Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe ògiri àti ààbò rẹ̀.
Dnia onego śpiewana będzie ta pieśń w ziemi Judzkiej: Mamy miasto obronne, Bóg zbawieniem opatrzył mury i baszty jego.
2 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé, orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
Otwórzcie bramy, a niech wnijdzie naród sprawiedliwy, który strzeże prawdy.
3 Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin, nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Człowieka spolegającego na tobie zachowywasz w pokoju, w pokoju mówię: bo w tobie ufa.
4 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé, nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta ayérayé náà.
Miejcie nadzieję w Panu aż na wieki; boć w Panu, w Panu jest skała wieczna.
5 Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀ ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀; ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Ale poniża mieszkającego na wysokości; miasto wyniosłe poniża, poniża je aż do ziemi, i strąca je aż do prochu;
6 Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ẹsẹ̀ aninilára n nì, ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.
Depcze je noga; nogi ubogiego, stopa nędzników.
7 Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú, ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà àwọn olódodo ṣe geere.
Ścieszka sprawiedliwego jest prosta; prostą drogą sprawiedliwego wyrównywasz.
8 Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ àwa dúró dè ọ́; orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
Na drodze sądów twoich, Panie! oczekujemy cię; żądność duszy naszej jest do imienia twego, i do wspominania na cię.
9 Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru; ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ. Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
Dusza moja żąda cię w nocy, owszem, duchem swym, który jest we mnie, rano cię szukam; albowiem gdy się sądy twoje odprawiają na ziemi, sprawiedliwości się uczą obywatele okręgu ziemskiego.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà wọn kò kọ́ láti sọ òdodo; kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
Gdy się łaska pokazuje niepobożnemu, nie uczy się sprawiedliwości; w ziemi prawości nieprawość czyni, a nie dba nic na majestat Pański.
11 Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ṣùgbọ́n àwọn kò rí i. Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ kí ojú kí ó tì wọ́n; jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn ọ̀tá rẹ jó wọn run.
Panie! choć wywyższona jest ręka twoja, przecię tego nie widzą; ujrząć, ale pohańbieni będą, zajrząc ludowi twemu; nadto i ogień tych nieprzyjaciół twoich pożre.
12 Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa; ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni ó ṣe é fún wa.
Panie! zrządzisz nam pokój; bo wszystko, co się działo przy nas, czyniłeś ku dobremu naszemu.
13 Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí, ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
Panie Boże nasz! panowalić nad nami inni panowie oprócz ciebie; ale myśmy tylko, w tobie ufając, wspominali na imię twoje.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́; gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́. Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán, ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
Pomarli, nie ożyją; martwymi będąc nie powstaną, przeto, żeś ich nawiedził i wykorzenił, i wygładził wszystkę pamiątkę ich.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa; ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i. Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ; ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.
Rozmnożyłeś naród; o Panie! rozmnożyłeś naród; uwielbionyś jest, acześ go był zapędził na wszystkie granice ziemi.
16 Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn; nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn, wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
Panie! w ucisku szukali cię; gdyś ich karał, wylewali modlitwy swe.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
Jako brzemienna, gdy się przybliża ku rodzeniu, boleje i woła w boleściach swoich, takeśmy byli przed obliczem twojem, Panie!
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora, ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ. Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé; àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.
Poczęliśmy, boleliśmy; aleśmy tylko jakoby wiatr porodzili, a żadnegośmy wybawienia ziemi nie sprawili, i nie upadli mieszkający na okręgu ziemskim.
19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè ara wọn yóò dìde. Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀, dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀. Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀, ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.
Ożyją umarli twoi, trupy moje wstaną, gdy rzeczesz: Ocućcie się, a śpiewajcie mieszkający w prochu! Albowiem rosa twoja będzie jako rosa na ziołach; ale niezbożnych o ziemię uderzysz.
20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín, ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀ títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
Idź, ludu mój! wnijdź do komór swoich, a zamknij drzwi twoje za sobą; skryj się na maluczką chwilkę, dokąd nie przeminie rozgniewanie.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀ láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀; kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.
Albowiem oto Pan wychodzi z miejsca swego, aby nawiedził nieprawość mieszkających na ziemi; tedy ziemia odkryje krew swoję, a nie zakryje dalej pobitych swoich.