< Isaiah 26 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda. Àwa ní ìlú alágbára kan, Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe ògiri àti ààbò rẹ̀.
در آن روز، این سرود در سرزمین یهودا خوانده خواهد شد: شهر ما قوی و محکم است و خدا با حصار نجاتبخش خود ما را حفظ می‌کند.
2 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé, orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
دروازه‌ها را بگشایید تا قوم عادل و با ایمان وارد شوند.
3 Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin, nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
ای خداوند، کسانی را که به تو توکل دارند و در عزم خود راسخند در آرامش کامل نگاه خواهی داشت.
4 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé, nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta ayérayé náà.
همیشه بر خداوند توکل کنید؛ او جان پناه جاودانی ماست!
5 Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀ ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀; ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
خدا اشخاص مغرور را پست گردانیده و شهر مستحکم آنان را با خاک یکسان کرده است.
6 Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ẹsẹ̀ aninilára n nì, ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.
کسانی که زیر ظلم و ستم بوده‌اند اینک پیروزمندانه بر خرابه‌های شهر قدم می‌گذارند و آن را لگدمال می‌کنند.
7 Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú, ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà àwọn olódodo ṣe geere.
راه درستکاران راست است؛ پس ای خدای راستی راه ایشان را هموار ساز.
8 Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ àwa dúró dè ọ́; orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
ای خداوند، ما از خواست تو پیروی می‌کنیم و به تو امید بسته‌ایم؛ اشتیاق قلب ما تنها تو هستی.
9 Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru; ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ. Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
شب را در اشتیاق تو به سر می‌برم و هنگام سپیده دم تو را می‌طلبم. هنگامی که تو جهان را داوری کنی آنگاه مردم مفهوم عدالت را خواهند آموخت.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà wọn kò kọ́ láti sọ òdodo; kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
هر چند تو نسبت به گناهکاران رحیم هستی، اما آنان هرگز یاد نمی‌گیرند که خوبی کنند. آنان در این سرزمین خوبان به بدکاری خود ادامه می‌دهند و به جلال و عظمت تو توجه نمی‌کنند.
11 Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ṣùgbọ́n àwọn kò rí i. Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ kí ojú kí ó tì wọ́n; jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn ọ̀tá rẹ jó wọn run.
دشمنانت نمی‌دانند که تو آنها را مجازات خواهی کرد. خداوندا، آنها را مجازات کن و نشان بده که قومت را دوست داری. بگذار سرافکنده شوند؛ بگذار در آتش خشم تو بسوزند.
12 Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa; ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni ó ṣe é fún wa.
خداوندا، می‌دانیم تو برای ما صلح و سلامتی به ارمغان خواهی آورد، زیرا تا به حال هر موفقیتی که کسب کرده‌ایم، در واقع تو به ما عنایت فرموده‌ای.
13 Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí, ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
ای خداوند، اربابان بسیاری بر ما حکومت کرده‌اند، اما ارباب واقعی ما تو هستی و ما تنها تو را پرستش خواهیم کرد.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́; gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́. Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán, ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
آنان مردند و از بین رفتند و دیگر هرگز باز نمی‌گردند. تو آنها را به سزای اعمالشان رساندی و نابود کردی و نامشان را از خاطرها محو ساختی.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa; ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i. Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ; ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.
ای خداوند، قوم خود را افزودی و مملکت ما را وسیع ساختی. این سبب شده است که تو معروف شوی و نامت بر سر زبانها بیفتد.
16 Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn; nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn, wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
خداوندا، تو قومت را تنبیه کردی و ایشان هنگام سختی، در خفا به درگاه تو دعا کردند.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
ای خداوند، ما در حضور تو مثل زن حامله‌ای هستیم که هنگام زاییدن درد می‌کشد و فریاد برمی‌آورد.
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora, ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ. Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé; àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.
هر چند حامله شده، درد کشیدیم، ولی چیزی نزاییدیم! نتوانستیم برای ساکنان زمین نجات به ارمغان آوریم، و به دنیا حیات ببخشیم.
19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè ara wọn yóò dìde. Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀, dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀. Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀, ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.
اما مردگان قوم تو زنده شده، از خاک برخواهند خاست؛ زیرا شبنم تو بر بدنهای ایشان خواهد نشست و به آنها حیات خواهد بخشید. کسانی که در خاک زمین خفته‌اند بیدار شده، سرود شادمانی سر خواهند داد.
20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín, ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀ títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
ای قوم من، به خانه‌های خود بروید و درها را پشت سر خود ببندید. مدت کوتاهی خود را پنهان کنید تا غضب خدا بگذرد.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀ láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀; kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.
زیرا خداوند از آسمان می‌آید تا مردم دنیا را به سبب گناهانشان مجازات کند. زمین تمام خونهای ریخته شده را آشکار خواهد ساخت و دیگر اجساد کشته‌شدگان را در خود پنهان نخواهد کرد.

< Isaiah 26 >