< Isaiah 26 >

1 Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda. Àwa ní ìlú alágbára kan, Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe ògiri àti ààbò rẹ̀.
Na rĩrĩ, mũthenya ũcio rwĩmbo rũrũ nĩruo rũkainwo bũrũri wa Juda: Tũrĩ na itũũra inene rĩa hinya; Ngai atuuaga ũhonokio ũtuĩke thingo ciarĩo na njirigo ciarĩo cia hinya.
2 Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé, orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
Hingũrai ihingo nĩguo rũrĩrĩ rũrĩa rũthingu rũtoonye, o rũrĩrĩ rũrĩa rũrũmagia wĩtĩkio.
3 Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin, nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Mũndũ ũrĩa ũrĩ meciiria makindĩirie harĩwe-rĩ, nĩwe ũgaatũũria na thayũ mũkinyanĩru tondũ nĩakwĩhokete.
4 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé, nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta ayérayé náà.
Tũũrai mwĩhokete Jehova nginya tene, nĩgũkorwo Jehova, o we Jehova, nĩwe Rwaro rwa Ihiga rwa tene na tene.
5 Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀ ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀; ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Nĩanyiihagia andũ arĩa maikaraga kũrĩa gũtũũgĩru, o na itũũra rĩrĩa itũũgĩru akarĩharũrũkia, akarĩharagania thĩ, agacooka akarĩtungumania rũkũngũ-inĩ.
6 Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ẹsẹ̀ aninilára n nì, ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.
Magũrũ ma andũ makarĩrangĩrĩria; magũrũ ma andũ arĩa ahinyĩrĩrie, o na makinya ma arĩa athĩĩni.
7 Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú, ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà àwọn olódodo ṣe geere.
Njĩra ya andũ arĩa athingu nĩ nũngĩrĩru; nawe Jehova, Wee Mũthingu, nĩwe ũnyorokagia njĩra cia arĩa athingu.
8 Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ àwa dúró dè ọ́; orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
Ĩĩ, ti-itherũ Jehova, nĩwe twetagĩrĩra o tũgĩthiiagĩra njĩra ya mawatho maku; ngoro ciitũ ciĩriragĩria rĩĩtwa rĩaku na ngumo yaku.
9 Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru; ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ. Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
Ngoro yakwa nĩwe ĩĩriragĩria ũtukũ; rũciinĩ roho wakwa ũgakũnyootera. Rĩrĩa watuanĩra ciira wa kĩhooto gũkũ thĩ, andũ a mabũrũri mothe nĩmerutaga ũhoro wa ũthingu.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà wọn kò kọ́ láti sọ òdodo; kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
O na andũ aaganu mangĩiguĩrwo tha, matiĩrutaga ũhoro wa ũthingu; o na marĩ bũrũri-inĩ wa arĩa arũngĩrĩru, mathiiaga o na mbere gwĩka ũũru, makaaga gũtĩĩa ũnene wa Jehova.
11 Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ṣùgbọ́n àwọn kò rí i. Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ kí ojú kí ó tì wọ́n; jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn ọ̀tá rẹ jó wọn run.
Wee Jehova-rĩ, guoko gwaku nĩ kwambararĩtio na igũrũ, no matingĩkuona o na atĩa. No rĩrĩ, reke mone kĩyo kĩrĩa ũrĩ nakĩo nĩ ũndũ wa andũ aku, nĩgeetha maconoke; mwaki ũrĩa ũigĩirwo thũ ciaku nĩũrekwo ũmacine.
12 Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa; ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni ó ṣe é fún wa.
Wee Jehova-rĩ, nĩwe ũtũheaga thayũ; maũndũ marĩa mothe tũhingĩtie, nĩwe ũtwĩkĩire.
13 Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí, ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
Wee Jehova, o Wee Ngai witũ, nĩ harĩ aathani angĩ manatwatha tiga wee, no rĩrĩ, rĩĩtwa rĩaku riiki norĩo tũtĩĩte.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́; gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́. Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán, ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
Na rĩrĩ, acio rĩu nĩmakuĩte, matigacooka gũtũũra muoyo; maroho macio matikariũka. Wee nĩwamaherithirie ũkĩmaananga; ningĩ ũgĩtũma mariganĩre biũ.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa; ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i. Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ; ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.
Wee Jehova nĩũtũmĩte rũrĩrĩ rũu ruongerereke; ti-itherũ nĩwongereire rũrĩrĩ rũu, ũkarũingĩhia. Wee nĩwĩgĩĩrĩire na riiri, ũkaaramia mĩhaka yothe ya bũrũri.
16 Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn; nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn, wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
Atĩrĩrĩ Jehova, mookire kũrĩ we rĩrĩa maarĩ na mathĩĩna; rĩrĩa wamaherithagia-rĩ, maahotaga o kũhooya na mĩheehũ.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
O ta ũrĩa mũndũ-wa-nja arĩ na nda akiriĩ gũciara enyogondaga na agakaya nĩ ruo-rĩ, ũguo noguo twatariĩ tũrĩ mbere yaku, Wee Jehova.
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora, ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ. Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé; àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.
Ithuĩ twatariĩ ta twarĩ nda, twenyogondaga nĩ ruo, no rĩrĩ, nĩ ta twaciarire o rũhuho. Gũtirĩ ũndũ o na ũrĩkũ wa kũhonokania twĩkĩte gũkũ thĩ, o na kana tũgaciara andũ arĩa maikaraga gũkũ thĩ.
19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè ara wọn yóò dìde. Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀, dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀. Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀, ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.
No rĩrĩ, andũ aku arĩa makuĩte nĩmagatũũra muoyo; mĩĩrĩ yao nĩĩkariũka. Inyuĩ arĩa mũtũũraga rũkũngũ-inĩ, ũkĩrai na mwanĩrĩre nĩ gũkena. Ime rĩanyu rĩtariĩ ta ireera rĩa rũciinĩ; nayo thĩ nĩĩgacookia andũ arĩa akuũ muoyo.
20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín, ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀ títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
Atĩrĩrĩ, inyuĩ andũ akwa, thiĩi mũtoonye tũnyũmba twanyu na mwĩhingĩre; mwĩhithe kuo gwa kahinda kanini nginya mangʼũrĩ make mathire.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀ láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀; kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.
Atĩrĩrĩ, Jehova nĩarooka oimĩte gĩikaro-inĩ gĩake, nĩguo aherithie andũ a gũkũ thĩ nĩ ũndũ wa mehia mao. Nayo thĩ nĩĩkonania thakame ĩrĩa ĩitĩtwo kuo; ndĩgaacooka kũhitha andũ ayo arĩa moragĩtwo.

< Isaiah 26 >