< Isaiah 24 >

1 Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé yóò sì pa á run òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́ yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—
Íme az Örökkévaló megüresíti és pusztává teszi a földet, felforgatja a színét és szétszórja lakóit
2 bákan náà ni yóò sì rí fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn, fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀, fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin, fún olùtà àti olùrà, fún ayáni àti atọrọ fún ayánilówó àti onígbèsè.
És olyan lesz a nép mint a pap, a szolga mint az úr, a szolgáló mint az úrnője, a vevő mint az eladó, a kölcsönadó mint a kölcsönvevő, a hitelező mint akinek hitelez.
3 Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run. Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.
Megüresedve megüresedik a föld és kifosztódva kifosztódik, mert az Örökkévaló mondta ki ezt az igét.
4 Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá, ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un, àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú
Gyászol, hervad; a föld, elfonnyad, elhervad a világ, elfonnyadnak a föld népének magasai.
5 àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́; wọ́n ti pa àwọn òfin run wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.
És a föld fertőzötté; lett a lakói alatt, mert megszegtek tanokat, megtörtek törvényt, megbontották az örök szövetséget.
6 Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run; àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn. Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù, àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.
Ezért átok emésztette a földet és bűnhődtek a rajta lakók; ezért megégtek a föld lakói és csekély számban maradt ember.
7 Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ, gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.
Gyászolt a must, fonnyadt a szőlő, sóhajtoznak a vígszívűek.
8 Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́ ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Megszűnt a dobok vigassága, elmaradt az ujjongók zaja, megszűnt a hárfa vigassága.
9 Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́ ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.
Dal mellett nem isznak majd bort, keserű lesz ivóinak a részegítő ital.
10 Ìlú tí a run ti dahoro, ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
Megtöretett a semmiség városa, elzáratott minden ház, nincs bemenés.
11 Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́, gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
Kiáltás van a borért az utcákon, lealkonyodott minden öröm, elköltözött a föld vigassága.
12 Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro, ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.
Maradt a városban pusztulás és rommá zúzatik szét a kapu.
13 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi, tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí a kórè èso tán.
Mert így lesz az a földön, a népek közepette, mint mikor leverik az olajfát, mint böngészéskor, ha vége van a szüretnek.
14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀; láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo ọláńlá Olúwa.
Amazok fölemelik hangjukat, ujjonganak, az Örökkévaló fensége miatt vigadnak a tenger felől.
15 Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa; gbé orúkọ Olúwa ga, àní Ọlọ́run Israẹli, ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun.
Ezért a fénytájakon tiszteljétek az Örökkévalót, a tenger szigetéin az Örökkévalónak, Izrael Istenének nevét.
16 Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin; “Ògo ni fún olódodo n nì.” Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé! “Ègbé ni fún mi! Alárékérekè dalẹ̀! Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
A föld széléről dalokat hallottunk: Díszt az igaznak. Én meg mondtam: végem van, végem van, jaj nekem; hűtlenek hűtlenkedtek és hűtlenséggel hűtlenkedtek a hűtlenek.
17 Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́, ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
Rettegés, örvény és tőr ellened, lakója a földnek!
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà yóò ṣubú sínú ihò, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú. Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
És lesz, aki futamodik a rettegés hangjától, beleesik az örvénybe, és aki feljön az örvényből, megfogatik a tőrben. Mert ablakrácsok a magasból megnyíltak és megrendültek a föld alapjai.
19 Ilẹ̀ ayé ti fọ́ ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù, a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.
Zúzva szétzúzódott a föld, morzsolva elmorzsolódott a föld, tántorodva megtántorodott a föld.
20 Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí, ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́; ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.
Inogva inog a föld, mint a részeges és megrázkódik mint a kaliba; rá nehezedik bűne, elesik és többé föl nem kel.
21 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.
És lesz azon napon, megbünteti az Örökkévaló a magasság seregét a magasságban és a föld királyait a földön.
22 A ó sì kó wọn jọ pọ̀, gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò, a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú, a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
És összegyűjtetnek, mint foglyokat gyűjtenek a börtönbe és elzáratnak zárt helyre; de sok nap után gondolnak rájuk.
23 A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn; nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu, àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.
És elpirul a hold és megszégyenül a nap, mert király lett az Örökkévaló, a seregek ura Czión hegyén és Jeruzsálemben, és vénei előtt dicsőség van.

< Isaiah 24 >