< Isaiah 24 >

1 Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé yóò sì pa á run òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́ yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—
A IA hoi, e hooneoneo ana o Iehova i ka aina, E anai ana oia ia ia; E hookahuli no oia ia ia, a e hoopuehu i kona poe e noho ana.
2 bákan náà ni yóò sì rí fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn, fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀, fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin, fún olùtà àti olùrà, fún ayáni àti atọrọ fún ayánilówó àti onígbèsè.
E hiki mai auanei keia, E like me kanaka, pela no ke kahuna; E like me ka kauwa kane, pela no kona haku kane; E like me ke kauwa wahine, pela no kona haku wahine; E like me ka mea kuai mai, pela no ka mea kuai aku; E like me ka mea noi, pela no ka mea haawi; E like me ka mea loaa ka ukuhoopanee, Pela no ka mea haawi i ka ukuhoopanee.
3 Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run. Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.
E hooneoneo loa ia ka aina, e anai loa ia'ku no, No ka mea, na Iehova i olelo mai ia olelo.
4 Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá, ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un, àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú
Ke kanikau nei ka aina, ua mae wale, Ua nawaliwali ka honua, ua mimino loa; Ua nawaliwali ka poe haaheo o ka aina.
5 àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́; wọ́n ti pa àwọn òfin run wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.
Ua hoohaumiaia ka aina malalo o ka poe i noho; No ka mea, ua ae lakou maluna o na kanawai, Ua hoololi i na olelopaa, Ua uhai lakou i ka berita mau loa.
6 Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run; àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn. Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù, àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.
Nolaila i pau ai ka aina i ka hooinoia, A ua hoopaiia ka poe e noho ana maluna ona; Nolaila e pau ai na kanaka o ka aina me he ahi la, Uuku hoi na kanaka e koe iho.
7 Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ, gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.
Ke waiho wale la no ka waina hou, Ua mae wale na kumu waina, O ka poe a pau i olioli ka naau, ua kaniuhu.
8 Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́ ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Ua oki ke kanikani olioli o na pahukani, Ua pau hoi ka olioli o ka poe olioli ana, Ua oki pu no hoi ke kanikani olioli o ka lira.
9 Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́ ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.
Aole lakou e inu hou i ka waina me ke oli; A e lilo ka wai ona i mea awaawa i ka poe nana e inu.
10 Ìlú tí a run ti dahoro, ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
Ua wawahiia ke kulanakauhale neoneo; Ua paniia na hale a pau, aohe mea komo iloko.
11 Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́, gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
He hooho no ka waina ma na alanui, Ua nalowale ka lealea a pau, Ua oki hoi ka olioli ana o ka aina.
12 Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro, ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.
E waiho ana no ke kulanakauhale me ka neoneo, Ua kani no ka wawahi ana o ka pukapa.
13 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi, tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí a kórè èso tán.
Pela no auanei mawaenakonu o ka aina, Mawaena hoi o na kanaka, E like me ka laau oliva i luluia, E like hoi me ka hooiliili hope ana, I ka wa i pau ai ka hua waina i ka ohiia.
14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀; láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo ọláńlá Olúwa.
Aka, e hookiekie no keia poe i ko lakou leo iluna, A e olioli aku, E hauoli lakou i ka nani o Iehova mai ke kai mai.
15 Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa; gbé orúkọ Olúwa ga, àní Ọlọ́run Israẹli, ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun.
Nolaila, e hoomana oukou ia Iehova, ma ka hikina, I ka inoa hoi o Iehova, ke Akua o ka Iseraela, ma na moku puni o ke kai.
16 Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin; “Ògo ni fún olódodo n nì.” Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé! “Ègbé ni fún mi! Alárékérekè dalẹ̀! Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
Ua lohe kakou i ke oli ana, mai ke kihi o ka honua mai, He nani ka poe i pono! I aku la no hoi au, Kuu make e, kuu make e! Auwe hoi au! Ke luku nei ka poe luku, O ka poe luku, ke luku nei, he luku ino.
17 Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́, ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
E ka mea e noho la ma ka aina, Aia maluna ou ka makau, a me ka lua, a me ka upiki.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà yóò ṣubú sínú ihò, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú. Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
O ka mea e holo, mai ka uwalaau o ka makau aku. E haule no ia ilalo i ka lua; A o ka mea e pii mai, mai loko mai o ka lua, E paa no ia iloko o ka upiki; No ka mea, ua hamama na puka wai o kulanihakoi, A ua naueue hoi na kumu o ka honua.
19 Ilẹ̀ ayé ti fọ́ ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù, a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.
Ua hoonaueue ino ia ka aina, Ua hoohelelei loa ia ka aina, Ua haalulu loa hoi ka aina.
20 Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí, ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́; ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.
Ua hikaka loa no ka aina, e like me ka mea i ona, Ua luliluli e like me ka moe lewa; Ua kaumaha no hoi kona hewa maluna ona, A hina no hoi ia, aole ala hou mai.
21 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.
A hiki aku ia la, E hoopai no o Iehova ma kahi kiekie i ka hewa o ka poe kiekie, A maluna o ka honua i ka hewa o na'lii o ka honua.
22 A ó sì kó wọn jọ pọ̀, gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò, a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú, a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
A e hoakoakoa pu ia lakou e like me ka poe paahao, no ka halepaahao; A e hoopaa loa ia lakou maloko o ka halepaahao; A mahope o na la he nui, e hoopaiia no lakou.
23 A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn; nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu, àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.
E hilahila no ka mahina, a e hilahila pu no me ka la; No ka mea, na Iehova o na kaua e noho alii, Maluna o ka mauna o Ziona, a ma Ierusalema, A ma ke alo o kona poe kahiko oia e hooleaia'i.

< Isaiah 24 >