< Isaiah 24 >

1 Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé yóò sì pa á run òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́ yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—
Voici, l’Eternel fait le vide et la solitude sur la terre, il en bouleverse la face et en disperse les habitants.
2 bákan náà ni yóò sì rí fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn, fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀, fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin, fún olùtà àti olùrà, fún ayáni àti atọrọ fún ayánilówó àti onígbèsè.
Un même sort atteint peuple et prêtre, esclave et maître, servante et maîtresse, acheteur et vendeur, prêteur et emprunteur, créancier et débiteur.
3 Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run. Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.
Elle est vidée à fond, la terre, complètement dépouillée: c’est l’Eternel qui a rendu cet arrêt.
4 Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá, ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un, àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú
La terre est attristée et flétrie, le monde est désolé et languissant, l’élite de la population est abattue.
5 àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́; wọ́n ti pa àwọn òfin run wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.
C’Est que la terre a été souillée par ses habitants: ils ont transgressé les lois, violé les statuts, rompu le pacte antique.
6 Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run; àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn. Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù, àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.
Aussi une malédiction dévore la terre, et ceux qui la peuplent, subissent le châtiment; les habitants de la terre sont consumés, et de rares mortels échappent.
7 Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ, gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.
Le vin est en deuil, la vigne est contristée, tous ceux qui avaient le cœur joyeux soupirent.
8 Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́ ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Adieu les gais tambourins, adieu la joie bruyante de ceux qui s’amusaient, adieu le plaisir de la harpe!
9 Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́ ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.
On ne boit plus de vin en chantant, les liqueurs fortes ont un goût amer pour les buveurs.
10 Ìlú tí a run ti dahoro, ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
Elle est brisée la cité promise au désordre, toute demeure est close, rendue inaccessible.
11 Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́, gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
Les cris, au sujet du vin, retentissent dans les rues, tout plaisir est voilé de tristesse, la gaieté est bannie de la terre.
12 Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro, ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.
Dans la ville, il ne reste que désolation, les portes sont fracassées et réduites en ruine.
13 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi, tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí a kórè èso tán.
Aussi il en sera de la terre, au sein des nations, comme des oliviers, après la récolte, comme des grappes oubliées, après vendanges faites.
14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀; láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo ọláńlá Olúwa.
Ceux-là élèveront la voix pour chanter, et, du côté de l’Ouest, éclateront en cris de joie devant la grandeur de l’Eternel.
15 Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa; gbé orúkọ Olúwa ga, àní Ọlọ́run Israẹli, ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun.
Oui, rendez hommage à l’Eternel dans les régions lumineuses, et, sur les côtes de la mer, proclamez le nom de l’Eternel, Dieu d’Israël.
16 Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin; “Ògo ni fún olódodo n nì.” Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé! “Ègbé ni fún mi! Alárékérekè dalẹ̀! Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
Du bout de la terre nous entendons des cantiques: "Gloire au juste!" Mais moi je dis: "La misère est mon lot, la misère est mon lot! Malheur à moi! Les violents exercent leurs violences, ils poussent au comble leurs violences.
17 Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́, ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
Epouvante, fosse et piège vous menacent, habitants de la terre.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà yóò ṣubú sínú ihò, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú. Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
Quiconque prend la fuite devant les cris, de l’épouvante tombe dans la fosse, et, s’il remonte du fond de la fosse, il est pris dans le filet: les écluses s’ouvrent dans les hauteurs célestes et les fondements de la—terre sont ébranlés.
19 Ilẹ̀ ayé ti fọ́ ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù, a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.
La terre éclate en se brisant, la terre tombe en pièces, la terre vacille étrangement.
20 Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí, ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́; ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.
La terre chancelle comme un homme ivre, elle est secouée comme une hutte; elle est écrasée sous le poids de son iniquité, elle tombe et ne peut plus se relever.
21 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.
En ce jour, l’Eternel châtiera les milices du ciel au ciel et les rois de la terre sur la terre.
22 A ó sì kó wọn jọ pọ̀, gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò, a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú, a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Ceux-ci seront réunis en tas comme des prisonniers au bord d’une fosse, ils seront enfermés dans la geôle; seulement, après de longs jours, on pensera à eux.
23 A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn; nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu, àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.
Et la lune sera couverte de honte, le soleil de confusion, car l’Eternel-Cebaot régnera alors sur la montagne de Sion et à Jérusalem, et sa gloire brillera aux yeux de ses anciens.

< Isaiah 24 >