< Isaiah 23 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Tire. Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi! Nítorí a ti pa Tire run láìsí ilé tàbí èbúté. Láti ilẹ̀ Saipurọsi ni ọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.
Brzemię Tyru. Zawódźcie, okręty Tarszisz, bo został zburzony tak, że nie ma ani domu, ani żadnego portu; oznajmiono im z ziemi Kittim.
2 Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù àti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sidoni, ẹ̀yin tí àwọn a wẹ Òkun ti sọ dọlọ́rọ̀.
Zamilczcie, mieszkańcy wyspy; którą napełnili kupcy Sydonu, przepływając przez morze.
3 Láti orí àwọn omi ńlá ni irúgbìn ìyẹ̀fun ti ilẹ̀ Ṣihori ti wá; ìkórè ti odò Naili ni owóòná Tire, òun sì ti di ibùjókòó ọjà fún àwọn orílẹ̀-èdè.
I ziarno Szichoru, [sprowadzane] przez wielkie wody, żniwo rzeki, było jego dochodem; był też rynkiem narodów.
4 Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Sidoni àti ìwọ àní ìwọ ilé ààbò ti Òkun, nítorí Òkun ti sọ̀rọ̀. “Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ rí Èmi kò tí ì wo àwọn ọmọkùnrin tàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
Wstydź się, Sydonie. Przemówiło bowiem morze, przemówiła twierdza morska: Nie wiję się w bólu ani nie rodzę, nie wychowuję młodzieńców ani nie odchowuję dziewic.
5 Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Ejibiti, wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípa ìròyìn láti Tire.
Jak na wieść o Egipcie tak będą się wić na wieść o Tyrze.
6 Kọjá wá sí Tarṣiṣi; pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
Przeprawcie się do Tarszisz, zawódźcie, mieszkańcy wyspy!
7 Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyá yín, ògbólógbòó ìlú náà, èyí tí ẹsẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọ láti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.
Czy to jest wasze wesołe miasto, którego historia sięga dawnych dni? Jego własne nogi zawiodą je na daleką wędrówkę.
8 Ta ló gbèrò èyí sí Tire, ìlú aládé, àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-aládé tí àwọn oníṣòwò wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míká ní orílẹ̀ ayé?
Kto powziął takie postanowienie przeciw Tyrowi, który rozdawał korony, którego kupcy są książętami, a jego handlarze – szanowanymi ziemi?
9 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀, láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ ba àti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́lá ilé ayé sílẹ̀.
PAN zastępów to postanowił, aby poniżyć pychę całej jego chwały i aby znieważyć wszystkich szanowanych ziemi.
10 Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò odò Ejibiti, ìwọ ọmọbìnrin Tarṣiṣi, nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.
Przeprawcie się przez swoją ziemię jak rzeka, o córko Tarszisz. Nie ma już siły.
11 Olúwa ti na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí Òkun ó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì. Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Kenaani pé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.
Wyciągnął swoją rękę nad morze, zatrząsnął królestwami. PAN wydał rozkaz przeciwko Kanaanowi, aby zburzyć jego twierdze;
12 Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́, ìwọ wúńdíá ti Sidoni, tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀ báyìí! “Gbéra, rékọjá lọ sí Saipurọsi, níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”
I powiedział: Już nie będziesz się weselić, ty zhańbiona dziewico, córko Sydonu. Powstań, przepraw się do Kittim; lecz i tam nie będziesz miała odpoczynku.
13 Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Babeli, àwọn ènìyàn tí kò jámọ́ nǹkan kan báyìí. Àwọn Asiria ti sọ ọ́ di ibùgbé àwọn ohun ẹranko aginjù; wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gùn wọn sókè, wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòhò wọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.
Oto ziemia Chaldejczyków – ten lud nie był [ludem]. Asyryjczyk założył ją dla mieszkańców pustyni. Wznieśli jej wieże, pobudowali jej pałace, ale on obrócił ją w gruzy.
14 Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!
Zawódźcie, okręty Tarszisz, gdyż wasza twierdza jest zburzona.
15 Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tire fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tire gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:
I stanie się w tym dniu, że Tyr pójdzie w zapomnienie na siedemdziesiąt lat, na okres dni jednego króla. A po upływie siedemdziesięciu lat Tyr będzie śpiewał jak nierządnica.
16 “Mú dùùrù kan, rìn kọjá láàrín ìlú, ìwọ àgbèrè tí a ti gbàgbé; lu dùùrù dáradára, kọ ọ̀pọ̀ orin, kí a lè ba à rántí rẹ.”
Weź harfę, obejdź miasto, zapomniana nierządnico! Graj ładnie, śpiewaj dużo, by przypomniano sobie ciebie.
17 Ní òpin àádọ́rin ọdún náà, Olúwa yóò bá Tire jà. Òun yóò sì padà sí àyálò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí panṣágà, yóò sì máa ṣe òwò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ ọba tí ó wà ní ilẹ̀ ayé.
I stanie się po upływie siedemdziesięciu lat, że PAN nawiedzi Tyr, a ten wróci do czerpania korzyści ze swego nierządu i będzie go uprawiał ze wszystkimi królestwami świata na powierzchni ziemi.
18 Síbẹ̀síbẹ̀ èrè rẹ̀ àti owó iṣẹ́ rẹ̀ ni a ó yà sọ́tọ̀ fún Olúwa; a kò ní kó wọn pamọ́ tàbí kí a há wọn mọ́wọ́. Ère rẹ̀ ni a ó fi fún àwọn tí ó ń gbé níwájú Olúwa, fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti aṣọ.
Lecz jego dochody i jego zysk będą poświęcone PANU. Nie będzie ich odkładać i gromadzić. Jego dochody będą dla tych, którzy przebywają przed PANEM, aby mogli jeść do syta i mieć dobre ubranie.

< Isaiah 23 >