< Isaiah 23 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Tire. Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi! Nítorí a ti pa Tire run láìsí ilé tàbí èbúté. Láti ilẹ̀ Saipurọsi ni ọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.
Amo sia: da Daia moilai bai bagade ea hou olelesa. Dilia dusagai ouligisu dunu hano wayabo bagadega ahoabe! Da: i dioiba: le, dinana huma! Dilia moilai bai bagade amo da wadela: lesi dagoi. Ea diasu amola ea dusagai ouligibi hano sogebi da wadela: lesi dagoi. Dilia da Saibalase asili, buhagisia, amo sia: nabimu.
2 Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù àti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sidoni, ẹ̀yin tí àwọn a wẹ Òkun ti sọ dọlọ́rọ̀.
Dilia Saidone liligi ligisisu diasu ouligisu dunu! Didigia: ma!
3 Láti orí àwọn omi ńlá ni irúgbìn ìyẹ̀fun ti ilẹ̀ Ṣihori ti wá; ìkórè ti odò Naili ni owóòná Tire, òun sì ti di ibùjókòó ọjà fún àwọn orílẹ̀-èdè.
Dilia da hano wayabo bagade degele, gagoma amo da Idibidi sogega fai amo bidi lamusa: , amola fifi asi gala ilima bidi lasu hamomusa: , dunu asunasi dagoi.
4 Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Sidoni àti ìwọ àní ìwọ ilé ààbò ti Òkun, nítorí Òkun ti sọ̀rọ̀. “Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ rí Èmi kò tí ì wo àwọn ọmọkùnrin tàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
Saidone moilai bai bagade fi! Dilia da gogosia: i dagoi. Hano wayabo bagade amola wayabo lugudu bagadedafa da di da elea mano hame sia: sa. Ilia da amane sia: sa, “Na da mano hame. Na da dunu mano amola uda mano hame fofosu.”
5 Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Ejibiti, wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípa ìròyìn láti Tire.
Dunu huluane, amola Idibidi dunu da Daia da wadela: lesi dagoi nabasea, fofogadigimu.
6 Kọjá wá sí Tarṣiṣi; pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
Dilia Founisia soge fi dunu! Se nababeba: le, huma! Siba: ini sogega hobeale masa: ne, logo hogoi helema.
7 Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyá yín, ògbólógbòó ìlú náà, èyí tí ẹsẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọ láti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.
Daia da hemonega hamone, hahawane ba: su. Be wali hahawane hame ba: sa. Daia moilai bai bagade fi da dunu amo hano wayabo degele, gaheabolo fi sogebi hahamoma: ne, asunasi. Be wali Daia da amo musa: gasa bagade amola hahawane moilai agoane hame ba: sa.
8 Ta ló gbèrò èyí sí Tire, ìlú aládé, àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-aládé tí àwọn oníṣòwò wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míká ní orílẹ̀ ayé?
Daia da musa: hina bagade ilia moilai. Amogawi esala hina bagade amoma osobo bagade fifi asi gala da baligiliwane nodosu. Be nowa da amo moilai noga: idafa amo wadela: musa: ilegebala: ?
9 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀, láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ ba àti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́lá ilé ayé sílẹ̀.
Hina Gode Bagadedafa da amo moilai wadela: musa: ilegei dagoi. Ilia da ilila: hamoiba: le, gasa fi hamosu. Amaiba: le, Hina Gode da amo gasa fi hou hedofamusa: , amola ilia dunu mimogo ilima eno dunu da nodosu amo fofonobomusa: , ilia moilai bai bagade wadela: musa: ilegei.
10 Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò odò Ejibiti, ìwọ ọmọbìnrin Tarṣiṣi, nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.
Dilia Siba: ini soge (amoga Founisia dunu da fimusa: asi) amo fi dunu dilia! Ifabi hamomusa: masa! Wali da dili gaga: ma: ne, dunu eno hame esala.
11 Olúwa ti na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí Òkun ó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì. Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Kenaani pé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.
Hina Gode da Ea lobo hano wayabo bagade amoga gadodili ilua: le, hina bagade ilia fi wadela: lesi dagoi. Ea sia: beba: le, Founisia bidi lasu moilai bai bagade bagohame da wadela: lesi.
12 Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́, ìwọ wúńdíá ti Sidoni, tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀ báyìí! “Gbéra, rékọjá lọ sí Saipurọsi, níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”
Saidone moilai bai bagade fi! Dilia hahawane hou da ebelei dagoi amola dilia fi dunu da banenesi dagoi ba: sa. Amabela: ? Ilia da Saibalase sogega hobeama: bela: ? Be amogawi ilia da gaga: su hame ba: mu.
13 Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Babeli, àwọn ènìyàn tí kò jámọ́ nǹkan kan báyìí. Àwọn Asiria ti sọ ọ́ di ibùgbé àwọn ohun ẹranko aginjù; wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gùn wọn sókè, wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòhò wọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.
(Asilia dunu hame be Ba: bilone dunu da sigua ohe fi Daia moilai bai bagade amo hasanasimusa: logo doasi dagoi. Ba: bilone dunu ilisu da moilai doagala: musa: diasu sedade gagula heda: i, amola Daia ea gaga: su gagoi mugululi, moilai bai bagade wadela: lesi dagoi.)
14 Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!
Dilia dusagai ouligisu dunu hano wayabo bagadega bila ahoabe! Se nababeba: le, huma! Moilai noga: i amo da dialoma: ne dilia da dafawaneyale dawa: i, amo da mugululi, wadela: lesi dagoi.
15 Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tire fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tire gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:
Eso da misunu, amoga Daia da gogolei dagoi ba: mu. Ode 70 amoga, (amo da hina bagade ea esalebe ode idi defele) dunu eno da Daia amo hame dawa: mu. Be ode 70 gidigisia, Daia da hina: da: i bidi lasu uda, amo ea hou da gesami amo ganodini dedei, amo defele ba: mu.
16 “Mú dùùrù kan, rìn kọjá láàrín ìlú, ìwọ àgbèrè tí a ti gbàgbé; lu dùùrù dáradára, kọ ọ̀pọ̀ orin, kí a lè ba à rántí rẹ.”
Gesami da agoane hea: sa: - “Di hame gagui hina: da: i bidi lasu uda! Dia sani baidama lale, moilai amo ganodini laloma. Hedema! Amola dia gesami amo dunu bu dima misa: ne bu hea: ma.”
17 Ní òpin àádọ́rin ọdún náà, Olúwa yóò bá Tire jà. Òun yóò sì padà sí àyálò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí panṣágà, yóò sì máa ṣe òwò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ ọba tí ó wà ní ilẹ̀ ayé.
Amo ode 70 gidigisia, Daia da ea musa: hawa: hamosu amoma buhagima: ne, Hina Gode da logo doasimu. Osobo bagade fifi asi gala huluane da ea bidi lasu liligi lamu.
18 Síbẹ̀síbẹ̀ èrè rẹ̀ àti owó iṣẹ́ rẹ̀ ni a ó yà sọ́tọ̀ fún Olúwa; a kò ní kó wọn pamọ́ tàbí kí a há wọn mọ́wọ́. Ère rẹ̀ ni a ó fi fún àwọn tí ó ń gbé níwájú Olúwa, fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti aṣọ.
Ea bidi lasu hamobeba: le, muni lasea, amo muni e da Hina Godema ima: ne momodale ligiagamu. E da amo muni udigili hame ligisimu, be nowa da Hina Godema nodone sia: ne gadosa da amo muni amoga ilia ha: i manu amola abula bidi lamu.

< Isaiah 23 >