< Isaiah 22 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ìran. Kí ni ó ń dààmú yín báyìí, tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
Alamǝt kɵrünüx berilgǝn jilƣa toƣrisida yüklǝngǝn wǝⱨiy: — Silǝr ⱨǝmminglar ɵgzilǝrning üstigǝ qiⱪiwalƣininglar zadi nemǝ ⱪilƣininglar?
2 Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò, ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
Silǝr huxalliⱪ dǝbdǝbisini kɵtüridiƣan, Warang-qurungƣa tolƣan yurt, Xadlinidiƣan xǝⱨǝr; Silǝrdin ɵltürülgǝnlǝr ⱪiliq bilǝn qepilƣan ǝmǝs, Yaki jǝnglǝrdǝ ɵlgǝn ǝmǝs;
3 Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ; a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà. Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀, lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà lọ́nà jíjìn réré.
Əmirliringlarning ⱨǝmmisi biraⱪla ⱪeqixti; Ular oⱪyasiz ǝsir boldi; Yiraⱪⱪa ⱪaqⱪan bolsimu, Silǝrdin tepiwelinƣanlarning ⱨǝmmisi birliktǝ ǝsir boldi.
4 Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi: jẹ́ kí n sọkún kíkorò. Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”
Xunga mǝn: — «Nǝziringlarni meningdin elinglar; Meni ⱪattiⱪ yiƣlaxⱪa ⱪoyunglar; Hǝlⱪimning bulinip ketixi toƣruluⱪ manga tǝsǝlli berixkǝ aldirap ɵzünglarni upratmanglar» — dedim.
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan tí rúkèrúdò àti rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ ní àfonífojì ìmọ̀, ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀ àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
Qünki samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigardin «Alamǝt kɵrünüx berilgǝn jilƣa»ning bexiƣa bir kün qüxidu, U bolsa awariqilik bolidiƣan, Ayaƣ asti ⱪilinip petiⱪdilidiƣan, Adǝmlǝr ⱪaymuⱪturulidiƣan, Sepil soⱪulup qeⱪilidiƣan, Taƣlarƣa ⱪarap yalwurup qirⱪiraydiƣan bir küni bolidu.
6 Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin, Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
Elam jǝng ⱨarwiliri wǝ adǝmliri bilǝn, atliⱪ ǝskǝrliri bilǝn oⱪdanni kɵtürüp kelidu, Kir bolsa ⱪalⱪanni eqip tǝyyar ⱪilidu.
7 Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun, àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.
Wǝ xundaⱪ boliduki, Əng güzǝl jilƣiliring jǝng ⱨarwiliri bilǝn tolup ketidu, Atliⱪ ǝskǝrlǝr dǝrwazang aldida sǝp tartip turidu.
8 Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò. Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù.
Ular Yǝⱨudaning üstidiki ⱪalⱪanni elip taxlaydu; Biraⱪ sǝn [Zion] xu künidǝ «Orman sarayi»diki ⱪorallarƣa ümid baƣliƣansǝn;
9 Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀, ìwọ ti tọ́jú omi sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
Silǝr Dawutning xǝⱨirining bɵsülgǝn jaylirining kɵp ikǝnlikini kɵrüp, Pǝstiki kɵlqǝk sulirini bir yǝrgǝ yiƣip su ambiri ⱪildinglar;
10 Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
Yerusalemdiki ɵylǝrni sanap, ulardin bǝzilirini buzup sepilni mustǝⱨkǝmlǝx üqün ixlǝttinglar,
11 Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì fún omi inú adágún àtijọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀ tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.
Xundaⱪla kona kɵlqǝktiki sularni ikki sepil otturisiƣa yiƣip ambar ⱪildinglar; Biraⱪ muxularni Yaratⱪuqiƣa ⱨeq ⱪarimidinglar, Burundin burun bularni Xǝkillǝndürüp Bekitküqigǝ ⱨeq ümid baƣlimidinglar!
12 Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun, pè ọ́ ní ọjọ́ náà láti sọkún kí o sì pohùnréré, kí o tu irun rẹ dànù kí o sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
Xu küni samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar silǝrni yiƣlap matǝm tutuxⱪa, Qaqni qüxürüp paynǝkbax boluxⱪa, Bɵz kiyim kiyixkǝ murajiǝt ⱪildi.
13 Ṣùgbọ́n wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà; màlúù pípa àti àgùntàn pípa, ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu! Ẹ̀yin wí pé, “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu, nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”
Biraⱪ bularning ornida, mana huxalliⱪ wǝ xadliⱪ, Kalilarni soyux, ⱪoylarni boƣuzlax, Gɵxlǝrni yeyix, xarablarni iqix, «yǝyli, iqǝyli, qünki ǝtǝ dunyadin ketimiz» — deyixlǝr boldi!
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar tǝripidin ⱪuliⱪimƣa ayan ⱪilindiki, «Bǝrⱨǝⱪ, muxu gunaⱨ silǝr ɵlmigüqǝ kǝqürülmǝydu» — dǝydu samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé, fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar mana xundaⱪ dǝydu: — «Barƣin, muxu ƣojidar, Ordini baxⱪuridiƣan muxu Xǝbnaning yeniƣa kirgin, uningƣa: —
16 Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín yìí àti pé ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín yìí, tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?
Sanga muxu yǝrdǝ nemǝ bar? Yaki muxu yǝrdǝ kiming bar? Birsi egizlikkǝ ɵzi üqün bir gɵr ⱪazƣandǝk, Ɵzi ⱪoram taxtin bir ⱪonalƣuni yonuƣandǝk, Ɵzüng üqün bir gɵr kolidingmu?
17 “Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí kí ó sì jù ọ́ nù, ìwọ ọkùnrin alágbára.
Mana ⱨǝy palwan, Pǝrwǝrdigar seni ɵz qanggiliƣa elip, qing siⱪimdap,
18 Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà— ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
Andin pomdaⱪtǝk seni bipayan, yiraⱪ bir zeminƣa taxliwetidu. Sǝn axu yǝrdǝ ɵlisǝn, Ⱨǝm axu yǝrdǝ ⱨǝywǝtlik jǝng ⱨarwiliringmu ⱪalidu, I ƣojangning jǝmǝtigǝ xǝrmǝndilik kǝltürgüqi!
19 Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ, a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.
Mǝn seni mǝnsipingdin eliwetimǝn, Xuning bilǝn seni ornungdin qüxüriwetimǝn.
20 “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah.
Xu künimu xundaⱪ boliduki, Mǝn Ⱨilⱪiyaning oƣli Ɵz ⱪulum bolƣan Eliakimni qaⱪirimǝn;
21 Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda.
Sening tonungni kiydürimǝn, Sening potang bilǝn uning belini qing ⱪilimǝn; Ⱨɵkümranliⱪingni uning ⱪoliƣa tapxurimǝn; Xuning bilǝn u Yerusalemdikilǝrgǝ wǝ Yǝⱨuda jǝmǝtigǝ ata bolidu.
22 Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí.
Dawut jǝmǝtining aqⱪuqini mǝn uning mürisidǝ ⱪoyimǝn; U aqsa, ⱨeqkim etǝlmǝydu, Ətsǝ, ⱨeqkim aqalmaydu.
23 Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.
Mǝn uni muⱪim bir jayƣa ⱪozuⱪ ⱪilip bekitimǝn; U bolsa atisining jǝmǝti üqün xǝrǝplik ⱨoⱪuⱪ-tǝht bolidu;
24 Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.
Hǝlⱪ uning üstigǝ atisining jǝmǝtining barliⱪ xɵⱨrǝtlirini yüklǝydu; Yǝni barliⱪ uruⱪ-nǝsillirini, Barliⱪ kiqik ⱪaqa-ⱪuqilarni, Piyalǝ-jamlardin tartip barliⱪ küp-idixlarƣiqǝ asidu.
25 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
Xu künidǝ — dǝydu samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar: — muⱪim jayƣa bekitilgǝn ⱪozuⱪ bolsa, egilip ketidu wǝ kesip taxlinidu; Uning üstigǝ esilƣan yüklǝr üzüp taxlinidu», — Qünki Pǝrwǝrdigar xundaⱪ degǝnidi.

< Isaiah 22 >