< Isaiah 22 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ìran. Kí ni ó ń dààmú yín báyìí, tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
Parole de la Vallée de Sion. D'où vient que maintenant vous êtes montés sur vos terrasses, disant des paroles
2 Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò, ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
Vaines? La ville est pleine de clameurs; tes blessés ne sont pas blessés par le glaive, et tes morts ne sont pas morts en combattant.
3 Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ; a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà. Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀, lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà lọ́nà jíjìn réré.
Tous tes princes sont en fuite; tes captifs sont durement enchaînés, et tes forts se sont réfugiés au loin.
4 Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi: jẹ́ kí n sọkún kíkorò. Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”
Et c'est pourquoi j'ai dit: Laissez-moi et je pleurerai amèrement; ne cherchez pas à me consoler, quand vient d'être brisée la fille de mon sang.
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan tí rúkèrúdò àti rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ ní àfonífojì ìmọ̀, ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀ àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
Car le jour du trouble et de la ruine, où tout est brisé et s'égare, vient du Seigneur Dieu des armées. Ils errent dans la vallée de Sion; du petit au grand ils errent sur les montagnes.
6 Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin, Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
Les Élamites ont pris leurs carquois; les cavaliers sont à cheval, les armées se rassemblent.
7 Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun, àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.
Et tes vallons préférés seront remplis de chars, et des cavaliers envahiront les portes de Juda,
8 Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò. Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù.
Et ils en ouvriront les portes; et ce jour-là ils pénètreront dans les demeures choisies de la cité;
9 Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀, ìwọ ti tọ́jú omi sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
Et, dans la citadelle de David, ils découvriront les endroits les plus cachés des maisons. Et ils ont vu combien elles sont nombreuses, et comme on a détourné l'eau de l'ancienne piscine pour ramener dans la ville,
10 Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
Et comme on a abattu les maisons de Jérusalem pour fortifier ses remparts.
11 Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì fún omi inú adágún àtijọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀ tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.
Et ainsi pour vous-mêmes, vous avez fait venir l'eau entre les deux enceintes, plus avant que l'ancienne piscine; mais vous n'avez point considéré celui qui, dès le principe, a bâti la ville, et vous n'avez point vu son Créateur.
12 Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun, pè ọ́ ní ọjọ́ náà láti sọkún kí o sì pohùnréré, kí o tu irun rẹ dànù kí o sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
Et le Seigneur, le Seigneur des armées, vous a en ce jour appelés à pleurer et à gémir, à vous raser la tête et à vous ceindre de cilices;
13 Ṣùgbọ́n wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà; màlúù pípa àti àgùntàn pípa, ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu! Ẹ̀yin wí pé, “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu, nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”
Mais eux, ils étaient en joie et en plaisirs à égorger des veaux, à immoler des brebis, à manger de la chair et à boire du vin, disant: Mangeons et buvons, car nous mourrons demain.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Et ces choses ont été révélées aux oreilles du Dieu des armées; car ce péché ne vous a pas été remis jusqu'à votre mort.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé, fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
Voici donc ce que dit le Seigneur Dieu des armées: Va trouver, au vestibule du temple, Somna, le trésorier, et dis-lui:
16 Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín yìí àti pé ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín yìí, tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?
Pourquoi es-tu ici, et qu'y fais-tu? Pourquoi as-tu taillé ici ton sépulcre? pourquoi l'as-tu placé sur un lieu élevé, et y as-tu creusé pour toi un lieu de repos?
17 “Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí kí ó sì jù ọ́ nù, ìwọ ọkùnrin alágbára.
Voilà qu'à présent le Seigneur Dieu des armées va chasser et briser cet homme; il va t'enlever ta robe
18 Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà— ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
Et ta couronne de gloire, et il te jettera dans une grande et immense campagne, et là tu mourras; et Dieu fera de ton char brillant un objet de honte, et le palais de ton prince sera foulé aux pieds;
19 Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ, a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.
Et tu seras renversé de ton rang et de ton ministère.
20 “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah.
Et ce jour-là j'appellerai mon serviteur Éliacim, fils d'Helcias,
21 Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda.
Et je le revêtirai de ta robe, et je lui donnerai ta couronne avec l'empire, et je confierai ton ministère à ses mains, et il sera comme un père pour ceux qui résident à Jérusalem et habitent en Judée.
22 Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí.
Et je lui donnerai la gloire de David, et il gouvernera, et il n'aura point de contradicteur;
23 Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.
Et je l'établirai prince en un lieu sûr, et il sera comme un trône de gloire pour la maison de son père.
24 Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.
Et tout homme en honneur dans la maison de son père, du petit au grand, mettra sa confiance en lui, et tous dépendront de lui.
25 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
En ce jour, voilà ce que dit le Seigneur Dieu des armées: L'homme qui avait été établi en un lieu sûr, y sera ébranlé; il en sera arraché, et il tombera, et sa gloire sera anéantie; parce qu'ainsi l'a dit le Seigneur.

< Isaiah 22 >