< Isaiah 22 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ìran. Kí ni ó ń dààmú yín báyìí, tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
The birthun of the valei of visioun. What also is to thee, for and al thou stiedist in to roouys,
2 Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò, ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
thou ful of cry, a citee of myche puple, a citee ful out ioiynge? thi slayn men weren not slayn bi swerd, nether thi deed men weren deed in batel.
3 Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ; a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà. Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀, lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà lọ́nà jíjìn réré.
Alle thi princes fledden togidere, and weren boundun harde; alle that weren foundun, weren boundun togidere, thei fledden fer.
4 Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi: jẹ́ kí n sọkún kíkorò. Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”
Therfor Y seide, Go ye awei fro me, Y schal wepe bittirli; nyle ye be bisie to coumforte me on the distriyng of the douyter of my puple.
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan tí rúkèrúdò àti rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ ní àfonífojì ìmọ̀, ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀ àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
For whi a dai of sleyng, and of defoulyng, and of wepyngis, is ordeined of the Lord God of oostis, in the valei of visioun; and he serchith the walle, and is worschipful on the hil.
6 Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin, Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
And Helam took an arowe caas, and the chare of an horse man; and the scheeld made nakid the wal.
7 Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun, àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.
And thi chosun valeis, Jerusalem, schulen be ful of cartis; and knyytis schulen putte her seetis in the yate.
8 Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò. Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù.
And the hilyng of Juda schal be schewid; and thou schalt se in that dai the place of armuris of the hous of the forest;
9 Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀, ìwọ ti tọ́jú omi sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
and ye schulen se the crasyngis of the citee of Dauid, for tho ben multiplied. Ye gaderiden togidere the watris of the lowere cisterne,
10 Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
and ye noumbriden the housis of Jerusalem, and ye distrieden housis, to make strong the wal; and ye maden a lake bitwixe twei wallis,
11 Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì fún omi inú adágún àtijọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀ tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.
and ye restoriden the watir of the elde sisterne; and ye biholden not to hym, that made `thilke Jerusalem, and ye sien not the worchere therof afer.
12 Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun, pè ọ́ ní ọjọ́ náà láti sọkún kí o sì pohùnréré, kí o tu irun rẹ dànù kí o sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
And the Lord God of oostis schal clepe in that dai to wepyng, and to morenyng, and to ballidnesse, and to a girdil of sak; and lo!
13 Ṣùgbọ́n wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà; màlúù pípa àti àgùntàn pípa, ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu! Ẹ̀yin wí pé, “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu, nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”
ioie and gladnesse is to sle caluys, and to strangle wetheris, to ete fleisch, and to drynke wyn; ete we, and drynke we, for we schulen die to morewe.
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
And the vois of the Lord of oostis is schewid in myn eeris, This wickidnesse schal not be foryouun to you, til ye dien, seith the Lord God of oostis.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé, fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
The Lord God of oostis seith these thingis, Go thou, and entre to hym that dwellith in the tabernacle, to Sobna, the souereyn of the temple; and thou schalt seie to hym,
16 Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín yìí àti pé ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín yìí, tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?
What thou here, ethir as who here? for thou hast hewe to thee a sepulcre here, thou hast hewe a memorial in hiy place diligentli, a tabernacle in a stoon to thee.
17 “Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí kí ó sì jù ọ́ nù, ìwọ ọkùnrin alágbára.
Lo! the Lord schal make thee to be borun out, as a kapoun is borun out, and as a cloth, so he shal reise thee.
18 Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà— ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
He crowninge schal crowne thee with tribulacioun; he schal sende thee as a bal in to a large lond and wijd; there thou schalt die, and there schal be the chare of thi glorie, and the schenschipe of the hous of thi Lord.
19 Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ, a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.
And Y schal caste thee out of thi stondyng, and Y schal putte thee doun of thi seruyce.
20 “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah.
And it schal be, in that dai Y schal clepe my seruaunt Eliachim, the sone of Helchie; and Y schal clothe hym in thi coote,
21 Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda.
and Y schal coumforte hym with thi girdil, and Y shal yyue thi power in to the hondis of hym; and he schal be as a fadir to hem that dwellen in Jerusalem, and to the hous of Juda.
22 Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí.
And Y schal yyue the keie of the hous of Dauyd on his schuldre; and he schal opene, and noon schal be that schal schitte; and he schal schitte, and noon schal be that schal opene.
23 Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.
And Y schal sette hym a stake in a feithful place, and he schal be in to the seete of glorie of the hous of his fadir.
24 Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.
And thou schalt hange on hym al the glorie of the hous of his fadir, diuerse kindis of vessels, eche litil vessel, fro the vesselis of cuppis `til to ech vessel of musikis.
25 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
In that dai, seith the Lord of oostis, the stake that was set in the feithful place, schal be takun awei, and it schal be brokun, and schal falle doun; and schal perische that hangide therynne, for the Lord spak.

< Isaiah 22 >