< Isaiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun. Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù, akógunjàlú kan wá láti aginjù, láti ilẹ̀ ìpayà.
Brzemię pustynnego morza. Jak wicher na południe nadciąga, tak przyjdzie z pustyni, ze strasznej ziemi.
2 Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù. Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn! Èmi yóò mú gbogbo ìpayínkeke dópin, ni ó búra.
Srogie widzenie jest mi pokazane. Zdrajca zdradza, niszczyciel niszczy. Nadciągnij, Elamie! Oblegaj, Medio! Położę kres wszelkiemu wzdychaniu.
3 Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí, ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti obìnrin tí ń rọbí, mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́, ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
Dlatego moje biodra są wypełnione bólem, ogarnęły mnie skurcze jak skurcze rodzącej. Wstrząśnięty jestem tym, co słyszę, przerażony tym, co widzę.
4 Ọkàn mí dàrú, ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi, ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí ti wá di ìpayà fún mi.
Zlękło się moje serce, strach mnie ogarnął. Noc moich rozkoszy zamieniła się w postrach.
5 Wọ́n tẹ́ tábìlì, wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká, wọ́n jẹ, wọ́n mu! Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé, ẹ fi òróró kún asà yín!
Przygotuj stół, niech strażnik trzyma straż; jedz, pij. Wstańcie, książęta, namaszczajcie tarcze.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Lọ, kí o bojúwòde kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
Tak bowiem powiedział mi Pan: Idź, postaw strażnika, niech mówi, co widzi.
7 Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin, àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ, jẹ́ kí ó múra sílẹ̀, àní ìmúra gidigidi.”
I zobaczył rydwan z dwoma jeźdźcami, który ciągnęły osły, i rydwan, który ciągnęły wielbłądy; i przypatrywał się im z wielką uwagą.
8 Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan, “Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán, a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
Wtedy zawołał [jak] lew: Panie mój! Stoję ciągle za dnia na wieży strażniczej; stoję na warcie całymi nocami.
9 Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí nínú kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin. Ó sì mú ìdáhùn padà wá: ‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú! Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀ ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’”
A oto nadciągają mężczyźni na rydwanie z dwoma jeźdźcami. I zawołał: Upadł, upadł Babilon i wszystkie rzeźbione posągi jego bogów roztrzaskane zostały o ziemię.
10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà, mo sọ ohun tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.
O moi wymłóceni i zboże mego klepiska! Co usłyszałem od PANA zastępów, Boga Izraela, to wam oznajmiłem.
11 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi. Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá, “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
Brzemię Dumy. Z Seiru ktoś woła do mnie: Strażniku, co [się stało] w nocy? Strażniku, co [się stało] w nocy?
12 Alóre náà dáhùn wí pé, “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú. Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè; kí o sì tún padà wá.”
Strażnik odpowiedział: Nadchodzi poranek, a także noc. Jeśli chcecie dopytywać, dopytujcie, nawróćcie się, przyjdźcie.
13 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia. Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani, tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
Brzemię na Arabię. W lasach Arabii będziecie nocować, wy, karawany Dedanitów.
14 gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ; ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema, gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
Niech mieszkańcy Tema wyjdą z wodą naprzeciw spragnionych, ze swoim chlebem niech wyjdą na spotkanie uciekającym.
15 Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà, kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ, kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ àti kúrò nínú ìgbóná ogun.
Będą bowiem uciekali przed mieczami, przed dobytym mieczem, przed napiętym łukiem, przed ciężką bitwą.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo ìlú Kedari yóò wá sí òpin.
Gdyż tak Pan powiedział do mnie: Za rok, liczony jak rok najemnika, ustanie cała chwała Kedaru.
17 Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun ìlú Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.
A reszta spośród łuczników, dzielni wojownicy spośród synów Kedaru, będzie zmniejszona. Tak bowiem powiedział PAN, Bóg Izraela.

< Isaiah 21 >