< Isaiah 21 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun. Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù, akógunjàlú kan wá láti aginjù, láti ilẹ̀ ìpayà.
Vision du désert. Comme une tempête venant de la terre passe de désert en désert, ainsi terrible
2 Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù. Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn! Èmi yóò mú gbogbo ìpayínkeke dópin, ni ó búra.
Et épouvantable une vision m'a été révélée: Le prévaricateur marche à ses prévarications, l'homme inique à ses iniquités. Sur moi viennent les Élamites, sur moi les anciens des Perses. Maintenant je gémirai et je me consolerai moi - même.
3 Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí, ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti obìnrin tí ń rọbí, mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́, ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
Voilà pourquoi mes reins ont défailli, et des douleurs comme celles de l'enfantement m'ont saisi. Ce que j'entends me fait mal, et je fais tout pour ne pas voir.
4 Ọkàn mí dàrú, ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi, ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí ti wá di ìpayà fún mi.
Mon cœur s'égare, l'iniquité m'inonde, mon âme succombe dans la terreur.
5 Wọ́n tẹ́ tábìlì, wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká, wọ́n jẹ, wọ́n mu! Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé, ẹ fi òróró kún asà yín!
Dressez la table, mangez, buvez. Levez-vous, princes, préparez vos boucliers;
6 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Lọ, kí o bojúwòde kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
Car voici ce que m'a dit le Seigneur: Va, place-toi en sentinelle, et ce que tu verras, publie-le.
7 Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin, àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ, jẹ́ kí ó múra sílẹ̀, àní ìmúra gidigidi.”
Et je vis deux cavaliers: un cavalier monté sur un âne, un autre sur un chameau. Écoute avec une grande attention,
8 Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan, “Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán, a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
Et appelle Urie au lieu d'observation. Ainsi dit le Seigneur. Et moi je me tins debout tout le jour, et je surveillai le camp toute la nuit.
9 Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí nínú kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin. Ó sì mú ìdáhùn padà wá: ‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú! Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀ ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’”
Et voilà que vint à moi un homme sur un char à deux chevaux. Et, répondant à ma demande, il dit: Elle est tombée, elle est tombée, Babylone; et toutes ses statues et toutes les œuvres de ses mains sont brisées contre terre.
10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà, mo sọ ohun tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.
Écoutez, ô vous qui êtes délaissés; et vous qui pleurez, écoutez ce que j'ai appris du Seigneur Dieu des armées, ce que m'a annoncé le Dieu d'Israël.
11 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi. Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá, “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
On me crie de Séir: Gardez les créneaux!
12 Alóre náà dáhùn wí pé, “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú. Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè; kí o sì tún padà wá.”
Je les garde dès le matin et durant la nuit. Si tu cherches un secours, cherche-le bien, et demeure près de moi.
13 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia. Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani, tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
Tu dormiras le soir dans la forêt sur le chemin de Daidan.
14 gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ; ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema, gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
Portez de l'eau à la rencontre de l'homme qui a soif; et vous qui habitez la terre de Théman, portez des pains au-devant de ceux qui fuient;
15 Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà, kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ, kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ àti kúrò nínú ìgbóná ogun.
Multitude d'hommes massacrés, multitude d'égarés, multitude de glaives et d'arcs tendus, multitude de guerriers tombés dans le combat.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo ìlú Kedari yóò wá sí òpin.
Car voici ce que m'a dit le Seigneur: Encore une année, une année de mercenaire, et la gloire des fils de Cédar sera effacée,
17 Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun ìlú Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.
Et il ne restera qu'un petit nombre des vaillants archers de Cédar. Ainsi dit le Seigneur, Dieu d'Israël.