< Isaiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun. Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù, akógunjàlú kan wá láti aginjù, láti ilẹ̀ ìpayà.
Le fardeau du désert de la mer. Alors que les tourbillons du Sud balaient le pays, cela vient du désert, d'une terre impressionnante.
2 Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù. Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn! Èmi yóò mú gbogbo ìpayínkeke dópin, ni ó búra.
Une vision douloureuse m'est annoncée. L'homme perfide est perfide, et le destructeur détruit. Monte, Elam, attaque! J'ai fait cesser tous les soupirs de la Médie.
3 Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí, ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti obìnrin tí ń rọbí, mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́, ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
Aussi mes cuisses sont-elles remplies d'angoisse. Des douleurs m'ont saisi, comme celles d'une femme en travail. Je souffre tellement que je ne peux pas entendre. Je suis si consternée que je ne vois pas.
4 Ọkàn mí dàrú, ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi, ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí ti wá di ìpayà fún mi.
Mon cœur bat la chamade. L'horreur m'a effrayé. Le crépuscule que je désirais s'est transformé en tremblement pour moi.
5 Wọ́n tẹ́ tábìlì, wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká, wọ́n jẹ, wọ́n mu! Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé, ẹ fi òróró kún asà yín!
Ils préparent la table. Ils font le guet. Ils mangent. Ils boivent. Levez-vous, princes, huilez le bouclier!
6 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Lọ, kí o bojúwòde kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
Car le Seigneur m'a dit: « Va, place une sentinelle. Qu'il dise ce qu'il voit.
7 Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin, àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ, jẹ́ kí ó múra sílẹ̀, àní ìmúra gidigidi.”
S'il voit une troupe, des cavaliers par deux, une troupe d'ânes, une troupe de chameaux, il écoutera avec une grande attention. »
8 Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan, “Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán, a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
Il cria comme un lion: « Seigneur, je me tiens continuellement sur la tour de guet pendant le jour, et chaque nuit je reste à mon poste.
9 Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí nínú kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin. Ó sì mú ìdáhùn padà wá: ‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú! Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀ ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’”
Voici qu'arrive une troupe d'hommes, des cavaliers par deux. » Il prit la parole et dit: « Elle est tombée, elle est tombée, Babylone, et toutes les images gravées de ses dieux sont brisées à terre.
10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà, mo sọ ohun tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.
Tu es mon battage, et le grain de mon sol! » Ce que j'ai entendu de la part de Yahvé des Armées, le Dieu d'Israël, je vous l'ai annoncé.
11 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi. Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá, “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
Le fardeau de Dumah. On m'appelle de Séir: « Sentinelle, que se passe-t-il dans la nuit? Sentinelle, qu'en est-il de la nuit? »
12 Alóre náà dáhùn wí pé, “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú. Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè; kí o sì tún padà wá.”
La sentinelle répondit: « Le matin vient, et aussi la nuit. Si tu veux t'informer, informe-toi. Reviens. »
13 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia. Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani, tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
La charge sur l'Arabie. Vous logerez dans les fourrés d'Arabie, caravanes de Dédanites.
14 gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ; ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema, gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
Ils apportaient de l'eau à celui qui avait soif. Les habitants du pays de Théma rencontrèrent les fugitifs avec leur pain.
15 Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà, kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ, kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ àti kúrò nínú ìgbóná ogun.
Car ils ont fui devant les épées, devant l'épée tirée, devant l'arc bandé, devant la chaleur du combat.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo ìlú Kedari yóò wá sí òpin.
Car l'Éternel m'a dit: « Dans un an, comme le compterait un ouvrier lié par contrat, toute la gloire de Kédar disparaîtra,
17 Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun ìlú Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.
et le reste du nombre des archers, des vaillants hommes des fils de Kédar, sera peu nombreux; car l'Éternel, le Dieu d'Israël, a parlé. »

< Isaiah 21 >