< Isaiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun. Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù, akógunjàlú kan wá láti aginjù, láti ilẹ̀ ìpayà.
Břímě pustého moře. Jako vichřice na poledne se žene, tak přijde z pouště, z země hrozné.
2 Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù. Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn! Èmi yóò mú gbogbo ìpayínkeke dópin, ni ó búra.
Vidění tvrdé jest mi ukázáno. Nešlechetník nešlechetnost páše, a zhoubce hubí. Přitáhniž Elame, Médský oblehni. Všelikému úpění jeho přestati rozkáži.
3 Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí, ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti obìnrin tí ń rọbí, mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́, ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
Z té příčiny naplněna jsou bedra má bolestí, úzkosti postihly mne jako úzkosti rodičky; sklíčen jsem, slyše to, strnul jsem, vida to.
4 Ọkàn mí dàrú, ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi, ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí ti wá di ìpayà fún mi.
Zkormoutilo se srdce mé, hrůza předěsila mne, noc mých rozkoší obrátila se mi v strach.
5 Wọ́n tẹ́ tábìlì, wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká, wọ́n jẹ, wọ́n mu! Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé, ẹ fi òróró kún asà yín!
Přistroj na stůl, nechť stráž drží strážný, jez, pí. Vstaňte knížata, mažte pavézy.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Lọ, kí o bojúwòde kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
Nebo tak řekl ke mně Pán: Jdi, postav strážného, kterýž by to, což uhlédá, oznámil.
7 Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin, àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ, jẹ́ kí ó múra sílẹ̀, àní ìmúra gidigidi.”
I viděl vozy, a dvěma řady jízdu, vozy, kteréž oslové, a vozy, kteréž velbloudové táhli; šetřil zajisté pilně s velikou bedlivostí.
8 Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan, “Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán, a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
A volal jako lev: Jáť, Pane můj, stojím na stráži ustavičně ve dne, nýbrž na stráži své já stávám v každičkou noc.
9 Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí nínú kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin. Ó sì mú ìdáhùn padà wá: ‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú! Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀ ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’”
(A aj, v tom přijeli na vozích muži a dvěma řady jízda.) Zvolal tedy a řekl: Padl, padl Babylon, a všecky rytiny bohů jeho o zem roztřískány.
10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà, mo sọ ohun tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.
Méť jest humno, a obilé humna mého. Což jsem slyšel od Hospodina zástupů, Boha Izraelského, oznámil jsem vám.
11 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi. Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá, “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
Břímě Dumy. Slyším hlas z Seir: Strážný, co bylo v noci? Strážný, co se stalo v noci?
12 Alóre náà dáhùn wí pé, “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú. Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè; kí o sì tún padà wá.”
Řekl strážný: Přišlo jitro, a tolikéž noc; chcete-li hledati, hledejte. Navraťte se, přiďte.
13 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia. Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani, tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
Břímě na Arabii. Po lesích v Arabii nocleh mívati budete, ó pocestní Dedanských.
14 gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ; ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema, gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
Obyvatelé země Tema nechať vynesou vody vstříc žíznivému; s chlebem jeho nechať vyjdou proti utíkajícímu.
15 Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà, kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ, kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ àti kúrò nínú ìgbóná ogun.
Nebo před mečem utíkati budou, před mečem vytaženým, před lučištěm nataženým, před těžkostí boje.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo ìlú Kedari yóò wá sí òpin.
Tak zajisté řekl Pán ke mně: Že po roce, jakýž jest rok nájemníka, přestane všecka sláva Cedar,
17 Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun ìlú Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.
A pozůstalý počet střelců udatných synů Cedar zmenšen bude; nebo Hospodin Bůh Izraelský to mluvil.

< Isaiah 21 >