< Isaiah 20 >

1 Ní ọdún tí olórí ogun, tí Sagoni ọba Asiria rán an, wá sí Aṣdodu, ó kọlù ú ó sì kó o—
Amy taoñe nanamea’ i Tartane i Asdodey, (ie nampañitrife’ ty mpanjaka’ i Asore), le nialia’e ty Asdode vaho tinava’e;
2 ní àkókò náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa ti ẹnu Isaiah ọmọ Amosi jáde. Ó sọ fún un pé, “Mú aṣọ ọ̀fọ̀ kúrò ní ara rẹ kí o sì bọ́ sálúbàtà kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀, ó ń lọ káàkiri ní ìhòhò àti láì wọ bàtà.
ie amy taoñe zay, le nitsara am’ Iesaià ana’ i Amotse t’Iehovà nanao ty hoe: Akia, abalaho hiafake an-toha’o eo i lamban-goniy vaho apolitiro am-pandia’o o hana’oo. Nanoe’e zay, nañavelo nihalo tsy aman-kana.
3 Lẹ́yìn náà ni Olúwa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ mi Isaiah ti lọ káàkiri ní ìhòhò àti láì wọ bàtà fún ọdún mẹ́ta, gẹ́gẹ́ bí àmì àti àpẹẹrẹ sí Ejibiti àti Kuṣi,
Le hoe t’Iehovà: Manahake te nañavelo tsy aman-tsaroñe, tsy aman-kana telo taoñe ty mpitoroko Iesaià, t’ie ho viloñe naho halatsañe amy Mitsraime naho amy Kose,
4 bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọba Asiria yóò kó àwọn ìgbèkùn Ejibiti lọ ní ìhòhò àti láì wọ bàtà pẹ̀lú àwọn àtìpó Kuṣi, ọ̀dọ́ àti àgbà, pẹ̀lú ìbàdí ìhòhò—bí àbùkù Ejibiti.
le ho kozozote’ ty mpanjaka’ i Asore o mpirohi’ i Mitsraimeo naho o hasese boake Koseo, hibongy vaho tsy ho aman-kana, ty kede naho ty bey, tsy ho aman-tsaro ty voli’e ho ami’ty hasalara’ i Mitsraime.
5 Gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Kuṣi tí wọ́n sì ń fi Ejibiti yangàn ni ẹ̀rù yóò dé bá tí a ó sì dójútì wọ́n.
Ho lonjetse naho meñatse iereo ty amy Kose, fitamà’ iareo, naho i Mitsraime fisengea’ iareo.
6 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn tí ó ń gbé ní etí Òkun yóò wí pé, ‘Wo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí àwọn tí a ti gbẹ́kẹ̀lé, àwọn tí a sá tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́ àti ìtúsílẹ̀ láti ọwọ́ ọba Asiria! Báwo ni a ó ṣe sálà?’”
Le hanao ty hoe ty mpimoneñe añ’olo-tane atoy amy andro zay: Heheke o nitamaen-tikañeo, i nipitsihan-tika nipay olotse hivotsoran-tika amy mpanjaka’ i Asoreiy; tika ‘nio! aia ty hivoratsahan-tika?

< Isaiah 20 >